< Psalms 5 >

1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi. Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa, kíyèsi àròyé mi.
Yahweh, listen to me while I pray! Pay attention to me when I am groaning [because I am suffering very much].
2 Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́, ọba mi àti Ọlọ́run mi, nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.
You are my King and my God. When I call to you to ask you to help me, listen to me, because you are the one to whom I pray.
3 Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi; ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀ èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
Listen to me when I pray to you [each] morning, and I wait for you to reply.
4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú; bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
You are not a god who is pleased with wicked people; you do not (associate with/invite into your house) [those who do what is] evil.
5 Àwọn agbéraga kò le è dúró níwájú rẹ̀. Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;
You do not allow those who are very proud to come to you to worship you. You hate all those who do evil things.
6 ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run. Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn ni Olúwa yóò kórìíra.
You get rid of liars, and you despise those who murder [others] and those who deceive [others].
7 Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀, èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀; ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.
Yahweh, because you love me so much and so faithfully, I come into your temple. I revere you greatly, and I bow down to worship you at your sacred temple.
8 Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi, mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.
Yahweh, because you act righteously toward me, show me what is right for me to do. Because I have many enemies, show me clearly what you want me to do.
9 Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́; ọkàn wọn kún fún ìparun. Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀; pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
My enemies never say what is true; they just want to destroy [others]. The things that they say [MTY] are [as foul as] an open grave [where a corpse is decaying]. They use their tongues to tell lies.
10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run! Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn. Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
O God, declare that they are guilty [MTY] [and punish them]. Cause them to experience the same disasters/troubles that they plan to cause to happen to others. Get rid of them because they have committed many sins, and they have rebelled against you.
11 Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀; jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí. Tan ààbò rẹ sórí wọn, àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.
But cause that all those who go to you to be protected will rejoice; cause them to sing joyfully to you forever. Protect those who love you [MTY]; they are truly happy because (of what you [do for them/they belong to] you).
12 Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo; ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.
Yahweh, you always bless those who act righteously; you protect them like a [soldier is protected by his] shield [SIM].

< Psalms 5 >