< Psalms 5 >

1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi. Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa, kíyèsi àròyé mi.
O Pakai, ka ocheng ho neingaipeh’in, Kalungthim a kataona jong neigelkhoh peh’in.
2 Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́, ọba mi àti Ọlọ́run mi, nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.
Panpi ngaija kakana neigelkhohpeh’in, kalengpa le ka Pathen; ajeh chu nangma kom’a bou taova kahi.
3 Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi; ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀ èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
O Pakai, jingkah teng kataona nei ngaipeh’in, jingkah seh leh nangma lam sangingtingkangaichat jouse nakom kahinlhut a kinemtah a ngah jingding kahi.
4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú; bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
Nangma thil phalouho chunga kipah ji Pahen nahipon, migilou ho jong na angsuna aumthei ji pouve.
5 Àwọn agbéraga kò le è dúró níwájú rẹ̀. Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;
Nangma angsunga mikiletsah ho adingjou jipon; Pakai nang man gitlou nale chonset bol jouse nathet soh hel e.
6 ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run. Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn ni Olúwa yóò kórìíra.
Nangin jouthu sei ho nasuh mang ding ahi; Pakai in mijoulhep holeh tolthat ho athet ahi.
7 Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀, èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀; ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.
Keima din vang, Nangailut na bulhingsetjal chun na hongsung hunglut nange; Chule nangma ginle jana a nahouin theng mai a bohkhup a chibai kabohding nahi.
8 Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi, mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.
O Pakai, kamelma ten eijo lounadin nalamdih a neipui in. Kamasanga um lampi hi kajuidih nadin neihin lhun jang peh in.
9 Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́; ọkàn wọn kún fún ìparun. Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀; pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
Ajeh chu kamelmate kamsung'a thutah apotthei tapon, asunglam’u jong setnajeng ahitai; Alol sung ujong lhankhuh abangin, alei ujong chuchi a kilhunglut kalbi abang e.
10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run! Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn. Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
O Pakai ama ho khu gotna petan. Aduhabol nauhi amaho lhuh na hihen! Achonsetnao ho jeh’in delmang jeng’in, ajeh chu amahohin nangma dounan na atong’un ahi.
11 Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀; jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí. Tan ààbò rẹ sórí wọn, àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.
Ahin koihileh nangma lhalim noi’a umho chu thanom’u hen! Nangma thangvahna lachu kipahtah’in sajingu hen! Amaho chunga nalhajah in hoidoh jing in lang, Nangma min ngailu jing ho jong kipa na lodim jing’u hen.
12 Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo; ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.
O Pakai, nang’in michonpha ho phatthei naboh tei in. Nalungtoh te ngailut na ompho phatah achun nahoibit jing e.

< Psalms 5 >