< Psalms 49 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn! Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.
Hlustið nú háir og lágir, ríkir og fátækir.
2 Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!
Allir heimsbúar hlýðið á.
3 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá
Ég tala til ykkar vísdómsorð.
4 èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe, èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.
Með undirleik hörpu kveð ég um hyggindi, veiti svör við spurningum lífsins:
5 Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé? Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,
Láttu ekki ógæfuna hræða þig, né óvini sem umkringja þig með illsku!
6 àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn, tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.
Auðæfum sínum treysta þeir og stæra sig af miklu ríkidæmi
7 Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀ padà tàbí san owó ìràpadà fún Ọlọ́run.
en þó gæti enginn þeirra greitt Guði lausnargjald fyrir bróður sinn, keypt hann lausan.
8 Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,
Sál mannsins er dýrmætari en svo að hún verði keypt fyrir fé.
9 ní ti kí ó máa wà títí ayé láìrí isà òkú.
Auður alls heimsins hrekkur ekki til að kaupa einum manni líf og forða honum frá gröfinni.
10 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú, bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
Þið auðmenn og vitringar og aðrir sem hreykið ykkur hátt, þið munuð farast eins og aðrir menn. Þið hafið enga kröfu til lífsins fremur en fífl og fáráðlingar. Þið verðið að eftirláta öðrum auð ykkar.
11 Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé, ibùgbé wọn láti ìrandíran, wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.
Hús og eignir bera nöfn ykkar rétt eins og þið ætlið að búa þar að eilífu!
12 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́ ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
Nei, maðurinn verður að deyja. Hann er eins og skepnurnar, þrátt fyrir frægð sína og frama.
13 Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó gbàgbọ́ nínú ara wọn, àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn, tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. (Sela)
Slík verða afdrif hinna hrokafullu en samt mun þeirra getið með virðingu þegar þeir eru dauðir.
14 Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú ikú yóò jẹun lórí wọn; ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò, jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀. Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́, isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn. (Sheol h7585)
En þeir fá ekki umflúið dauðann. Þegar upp er staðið verða hinir vondu að þjóna hinum góðu. Vald auðsins er þeim gagnslaust í dauðanum og ekki taka þeir auðæfi sín með sér. (Sheol h7585)
15 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà kúrò nínú isà òkú, yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀. (Sheol h7585)
En hvað um mig? Guð mun leysa sál mína frá dauða og frelsa mig úr helju. (Sheol h7585)
16 Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀. Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.
Vertu ekki gramur þótt einhver verði ríkur og reisi sér glæsihöll.
17 Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú, ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú.
Ekkert af því mun hann taka með sér í gröfina, ekki einu sinni frægð sína!
18 Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀. Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.
Í lifanda lífi telur hann sig heppinn og heimurinn klappar honum lof í lófa,
19 Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀ àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.
en þó deyr hann eins og aðrir og hverfur inn í myrkrið.
20 Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
Sá sem elskar eigin lofstír deyr eins og skepnan, þrátt fyrir frægð sína og frama.

< Psalms 49 >