< Psalms 49 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn! Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.
Pour le chef musicien. Un psaume par les fils de Korah. Écoutez ceci, vous tous, peuples. Écoutez, vous tous, habitants du monde,
2 Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!
à la fois basse et haute, les riches et les pauvres ensemble.
3 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá
Ma bouche prononcera des paroles de sagesse. Mon cœur exprimera la compréhension.
4 èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe, èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.
Je prêterai l'oreille à un proverbe. Je vais résoudre mon énigme sur la harpe.
5 Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé? Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,
Pourquoi aurais-je peur dans les jours de malheur? quand l'iniquité m'entoure à mes talons?
6 àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn, tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.
Ceux qui se confient en leurs richesses, et se vantent de la multitude de leurs richesses...
7 Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀ padà tàbí san owó ìràpadà fún Ọlọ́run.
aucun d'entre eux ne peut en aucune façon racheter son frère, ni donner à Dieu une rançon pour lui.
8 Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,
Car la rédemption de leur vie est coûteuse, aucun paiement n'est jamais suffisant,
9 ní ti kí ó máa wà títí ayé láìrí isà òkú.
pour qu'il vive à jamais, pour qu'il ne voie pas la corruption.
10 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú, bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
Car il voit que les sages meurent; de même, les fous et les insensés périssent, et laisser leur richesse à d'autres.
11 Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé, ibùgbé wọn láti ìrandíran, wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.
Leur pensée intérieure est que leurs maisons dureront toujours, et leurs demeures pour toutes les générations. Ils donnent leur nom à leurs terres.
12 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́ ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
Mais l'homme, malgré ses richesses, ne résiste pas. Il est comme les animaux qui périssent.
13 Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó gbàgbọ́ nínú ara wọn, àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn, tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. (Sela)
Tel est le destin de ceux qui sont insensés, et de ceux qui approuvent leurs paroles. (Selah)
14 Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú ikú yóò jẹun lórí wọn; ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò, jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀. Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́, isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn. (Sheol h7585)
Ils sont désignés comme un troupeau pour le séjour des morts. La mort sera leur berger. Le matin, les hommes intègres domineront sur eux. Leur beauté se décompose dans le séjour des morts, loin de leur manoir. (Sheol h7585)
15 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà kúrò nínú isà òkú, yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀. (Sheol h7585)
Mais Dieu rachètera mon âme de la puissance du séjour des morts, car il me recevra. (Selah) (Sheol h7585)
16 Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀. Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.
N'ayez pas peur quand un homme s'enrichit, quand la gloire de sa maison sera accrue;
17 Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú, ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú.
car lorsqu'il mourra, il n'emportera rien. Sa gloire ne descendra pas après lui.
18 Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀. Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.
Bien que de son vivant, il ait béni son âme... et les hommes te louent quand tu fais du bien à toi-même...
19 Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀ àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.
il ira à la génération de ses pères. Ils ne verront jamais la lumière.
20 Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
Un homme qui a des richesses sans comprendre, est comme les animaux qui périssent.

< Psalms 49 >