< Psalms 49 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn! Ẹ fi etí sí i, gbogbo ẹ̀yin aráyé.
Přednímu kantoru z synů Chóre, žalm. Slyšte to všickni národové, pozorujte všickni obyvatelé zemští.
2 Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré tálákà àti ọlọ́lá pẹ̀lú!
Tak z lidu obecného, jako z povýšených, tak bohatý, jako chudý.
3 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, èrò láti ọkàn mi yóò mú òye wá
Ústa má mluviti budou moudrost, a přemyšlování srdce mého rozumnost.
4 èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe, èmi yóò ṣí ọ̀rọ̀ ìkọ̀kọ̀ mi sílẹ̀ lójú okùn dùùrù.
Nakloním k přísloví ucha svého, a při harfě vykládati budu přípovídku svou.
5 Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé? Nígbà tí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ajinnilẹ́sẹ̀ mi yí mi ká,
I proč se báti mám ve dnech zlých, aby nepravost těch, kteříž mi na paty šlapají, mne obklíčiti měla?
6 àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn, tí wọn sì ń ṣe ìlérí ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ wọn.
Kteříž doufají v svá zboží, a množstvím bohatství svého se chlubí.
7 Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀ padà tàbí san owó ìràpadà fún Ọlọ́run.
Žádný bratra svého nijakž vykoupiti nemůže, ani Bohu za něj dáti mzdy vyplacení,
8 Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye kò sì sí iye owó tó tó fún sísan rẹ̀,
(Neboť by velmi drahé musilo býti vyplacení duše jejich, protož nedovedeť toho na věky),
9 ní ti kí ó máa wà títí ayé láìrí isà òkú.
Aby živ byl věčně, a neviděl porušení.
10 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú, bẹ́ẹ̀ ni aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n pẹ̀lú ṣègbé wọ́n sì fi ọrọ̀ wọn sílẹ̀ fún ẹlòmíràn.
Nebo se vídá, že i moudří umírají, blázen a hovadný člověk zaroveň hynou, zboží svého i cizím zanechávajíce.
11 Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé, ibùgbé wọn láti ìrandíran, wọn sọ orúkọ ilẹ̀ wọn ní orúkọ ara wọn.
Myšlení jejich jest, že domové jejich věční jsou, a příbytkové jejich od národu do pronárodu; pročež je po krajinách nazývají jmény svými.
12 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́ ó sì dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
Ale člověk v slávě netrvá, jsa podobný hovadům, kteráž hynou.
13 Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó gbàgbọ́ nínú ara wọn, àti àwọn tí ń tẹ̀lé wọn, tí ó gba ọ̀rọ̀ wọn. (Sela)
Taková snažnost jejich jest bláznovstvím při nich, však potomci jejich ústy svými to schvalují. (Sélah)
14 Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú ikú yóò jẹun lórí wọn; ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni yóò, jẹ ọba lórí wọn ní òwúrọ̀. Ẹwà wọn yóò díbàjẹ́, isà òkú ni ibùgbé ẹwà wọn. (Sheol h7585)
Jako hovada v pekle skladeni budou, smrt je žráti bude, ale upřímí panovati budou nad nimi v jitře; způsob pak oněchno aby zvetšel, z příbytku svého octnou se v hrobě. (Sheol h7585)
15 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà kúrò nínú isà òkú, yóò gbé mi lọ sọ́dọ̀ òun fún rara rẹ̀. (Sheol h7585)
Ale Bůh vykoupí duši mou z moci pekla, když mne přijme. (Sélah) (Sheol h7585)
16 Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀. Nígbà tí ìyìn ilé rẹ̀ ń pọ̀ sí i.
Neboj se, když by někdo zbohatl, a když by se rozmnožila sláva domu jeho.
17 Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú, ògo rẹ̀ kò ní bá a sọ̀kalẹ̀ sí ipò òkú.
Při smrti zajisté ničeho nevezme, aniž sstoupí za ním sláva jeho.
18 Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀. Àwọn ènìyàn yìn ọ́ nígbà tí ìwọ ṣe rere.
Ačťkoli duši své, pokudž jest živ, lahodí; k tomu chválí jej i jiní, když sobě čistě povoluje:
19 Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀ àwọn tí ki yóò ri ìmọ́lẹ̀ ayé.
A však musí se odebrati za věkem otců svých, a na věky světla neuzří.
20 Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.
Summou: Èlověk jsa ve cti, neusrozumí-li sobě, bývá učiněn podobný hovadům, kteráž hynou.

< Psalms 49 >