< Psalms 48 >

1 Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Ẹni ńlá ní Olúwa, tí ó sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
Pesem in psalm naslednikom Koretovim. Velik je Gospod in hvaljen silno, v mestu Boga našega, na gori svetosti svoje:
2 Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀, ayọ̀ gbogbo ayé, òkè Sioni, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
V lepoti kraja, veselji vse zemlje, na gori Sijonski, na severni strani v mestu kralja vélikega.
3 Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀; ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
Bog v dvorih njegovih spoznava se za grad.
4 Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀, wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
Ker, glej, sešli so se kralji, šli so vkup.
5 Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n, a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
Sami so videli, vkup so strmeli, zmedli so se, izbežali urno.
6 Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀, ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
Trepet jih je obšel tam, bolečina kakor porodnico.
7 Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi, wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
Z burjo razbijaš ladije morske.
8 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwa rí, ní inú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ìlú Ọlọ́run wa, Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. (Sela)
Kakor smo slišali, tako smo videli v mestu Gospoda vojnih krdél, v mestu Boga našega; Bog ga utrjuje na veke.
9 Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run, àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Milost tvojo premišljamo, o Bog, sredi tvojega svetišča.
10 Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run, ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé, ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
Kakor ime tvoje, tako je slava tvoja noter do krajev zemlje; pravice je polna desnica tvoja.
11 Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀ kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn nítorí ìdájọ́ rẹ.
Veselí se naj gora Sijonska, radujejo se hčere Judove zavoljo sodeb tvojih.
12 Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀, ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
Obhajajte Sijon, in obdajajte ga; štejte stolpe njegove.
13 Kíyèsi odi rẹ̀, kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀ kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
Upirajte misli svoje na trdnjavo, povzdignite oči k dvorom njegovim, da oznanjate prihodnjemu rodu.
14 Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé, Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.
Ker ta je naš Bog na vedno večne čase; ta nas bode vodil noter do smrti.

< Psalms 48 >