< Psalms 48 >

1 Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Ẹni ńlá ní Olúwa, tí ó sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
Pieśń psalmu synów Korego. Wielki jest Pan, i bardzo chwalebny w mieście Boga naszego, na górze świętej swojej.
2 Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀, ayọ̀ gbogbo ayé, òkè Sioni, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
Ozdobą krainy, uciechą wszystkiej ziemi jest góra Syon w stronach północnych, miasto króla wielkiego.
3 Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀; ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
Bóg w pałacach jego uznany jest za twierdzę wysoką.
4 Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀, wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
Bo oto królowie, gdy się zgromadzili i ciągnęli wespół,
5 Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n, a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
Sami to ujrzawszy bardzo się zadziwili, a przestraszeni będąc prędko uciekali.
6 Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀, ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
Strach ich tam ogarnął i boleść, jako niewiastę rodzącą.
7 Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi, wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
Wiatrem wschodnim pokruszysz okręty z Tarsys.
8 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwa rí, ní inú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ìlú Ọlọ́run wa, Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. (Sela)
Jakośmy słyszeli, takeśmy widzieli w mieście Pana zastępów, w mieście Boga naszego; Bóg je ugruntował aż na wieki. (Sela)
9 Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run, àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Uważamy, o Boże! miłosierdzie twoje w pośród kościoła twego.
10 Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run, ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé, ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
Jakie jest imię twoje, Boże! taka też jest chwała twoja aż do kończyn ziemi; sprawiedliwości pełna jest prawica twoja.
11 Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀ kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn nítorí ìdájọ́ rẹ.
NIech się rozweseli góra Syon: niech się rozradują córki Judzkie dla sądów twoich, Boże!
12 Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀, ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
Otoczcie Syon, i obstąpcie go; policzcie wieże jego.
13 Kíyèsi odi rẹ̀, kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀ kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
Przypatrujcie się pilnie basztom jego, a oglądajcie pałace jego, abyście umieli powiadać narodowi potomnemu.
14 Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé, Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.
Że ten Bóg jest Bogiem naszym na wieki wieczne, a iż on naszym hetmanem będzie aż do śmierci.

< Psalms 48 >