< Psalms 48 >

1 Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Ẹni ńlá ní Olúwa, tí ó sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
Koraha bērnu dziesma. Dziedātāju vadonim. Tas Kungs ir liels un ļoti teicams mūsu Dieva pilsētā Viņa svētā kalnā.
2 Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀, ayọ̀ gbogbo ayé, òkè Sioni, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
Jauki paceļas Ciānas kalns, visas zemes prieks, ziemeļa pusē, tā lielā Ķēniņa pilsēta.
3 Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀; ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
Dievs viņas pilīs ir atzīts par patvērumu.
4 Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀, wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
Jo redzi, ķēniņi sapulcējās un atnāca kopā;
5 Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n, a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
Tie redzēja un brīnījās, tie iztrūcinājās un steidzās projām.
6 Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀, ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
Drebēšana tos tur aizņēma, mokas tā kā sievu bērnu sāpēs.
7 Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi, wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
Tu sadauzi lielos jūras kuģus caur austriņu.
8 Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwa rí, ní inú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ìlú Ọlọ́run wa, Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. (Sela)
Tā kā bijām dzirdējuši, tā to esam redzējuši Tā Kunga Cebaot pilsētā, mūsu Dieva pilsētā. Dievs to stiprinās mūžīgi. (Sela)
9 Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run, àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Ak Dievs, mēs pieminam Tavu žēlastību Tavā svētā namā.
10 Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run, ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé, ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
Ak Dievs, tā kā Tavs vārds, tāpat ir Tava slava līdz pasaules galam, Tava labā roka ir taisnības pilna.
11 Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀ kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn nítorí ìdájọ́ rẹ.
Lai Ciānas kalns priecājās un Jūda meitas lai līksmojās Tavu tiesu labad.
12 Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀, ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
Ejat ap Ciānu un apmetaties ap viņu, skaitiet viņas torņus.
13 Kíyèsi odi rẹ̀, kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀ kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
Liekat vērā viņas mūrus, apraugāt viņas augstos namus, ka pēcnākamiem radiem to varat izteikt.
14 Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé, Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.
Jo šis Dievs ir mūsu Dievs mūžīgi mūžam. Viņš mūs vadīs līdz mūža galam.

< Psalms 48 >