< Psalms 47 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
¡Pueblos todos, aplaudan! ¡Aclamen a ʼElohim con voz de júbilo!
2 Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
Porque Yavé el ʼElyón es temible, Rey grande sobre toda la tierra.
3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
Él somete los pueblos a nosotros, Las naciones bajo nuestros pies.
4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
Él nos eligió nuestra herencia, El Esplendor de Jacob, a quien amó. (Selah)
5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
ʼElohim asciende con aclamación de júbilo, Yavé con sonido de trompeta.
6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
¡Canten a ʼElohim, canten! ¡Canten a nuestro Rey, canten!
7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
Porque ʼElohim es el Rey de toda la tierra. ¡Canten con entendimiento!
8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
¡ʼElohim reina sobre las naciones! ¡ʼElohim se sienta en su santo trono!
9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.
Los jefes de las naciones se reúnen como pueblo del ʼElohim de Abraham, Porque de ʼElohim son los escudos de la tierra, Él es sumamente exaltado.

< Psalms 47 >