< Psalms 47 >
1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
Para o músico chefe. Um salmo pelos filhos de Corá. Oh batam palmas, todos vocês nações. Grite a Deus com a voz do triunfo!
2 Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
Para Yahweh Most High é fantástico. Ele é um grande rei sobre toda a terra.
3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
Ele submete as nações sob nosso comando, e as pessoas sob nossos pés.
4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
Ele escolhe nossa herança para nós, a glória de Jacob, a quem ele amava. (Selah)
5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
God foi para cima com um grito, Yahweh com o som de uma trombeta.
6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
Sing elogia a Deus! Cante louvores! Cantemos louvores ao nosso Rei! Cantem louvores!
7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
Pois Deus é o Rei de toda a terra. Cante louvores com compreensão.
8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
Deus reina sobre as nações. Deus se senta em seu trono sagrado.
9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.
Os príncipes dos povos estão reunidos, o povo do Deus de Abraão. Pois os escudos da terra pertencem a Deus. Ele é muito exaltado!