< Psalms 47 >
1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
Przewodnikowi chóru. Psalm dla synów Korego. Klaszczcie w dłonie, wszystkie narody, wykrzykujcie Bogu radosnym głosem.
2 Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
Gdyż PAN Najwyższy budzi grozę, [jest] wielkim Królem nad całą ziemią.
3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
Podda nam ludzi i narody pod nasze stopy.
4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
Wybrał nam nasze dziedzictwo, chlubę Jakuba, którego umiłował. (Sela)
5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
Wstąpił Bóg wśród okrzyków, PAN przy dźwięku trąby.
6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
Śpiewajcie Bogu, śpiewajcie; śpiewajcie naszemu Królowi, śpiewajcie.
7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
Bóg bowiem [jest] Królem całej ziemi, śpiewajcie pieśni pouczające.
8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
Bóg króluje nad narodami, Bóg zasiada na swym świętym tronie.
9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.
Władcy narodów zebrali się z ludem Boga Abrahama, bo do Boga [należą] tarcze ziemi; on jest wielce wywyższony.