< Psalms 47 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
To the choirmaster - of [the] sons of Korah a psalm. O all the peoples strike a palm shout for joy to God with [the] sound of a shout of joy.
2 Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
For Yahweh [the] Most High [is] to be feared a king great over all the earth.
3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
He subdues peoples under us and peoples under feet our.
4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
He chooses for us inheritance our [the] pride of Jacob whom he loved (Selah)
5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
He has gone up God with a shout of joy Yahweh with [the] sound of a ram's horn.
6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
Sing praises to God sing praises sing praises to king our sing praises.
7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
For [is] [the] king of all the earth God sing praises a poem.
8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
He reigns God over nations God he sits - on [the] throne of holiness his.
9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.
Noble [people] of peoples - they have gathered [the] people of [the] God of Abraham for [belong] to God [the] shields of earth exceedingly he is exalted.

< Psalms 47 >