< Psalms 47 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.
For the Chief Musician; a Psalm of the sons of Korah. O clap your hands, all ye peoples; shout unto God with the voice of triumph.
2 Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó ọba ńlá lórí gbogbo ayé.
For the LORD Most High is terrible; he is a great King over all the earth.
3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa
He shall subdue the peoples under us, and the nations under our feet.
4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa, ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.
He shall choose our inheritance for us, the excellency of Jacob whom he loved. (Selah)
5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀, Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.
God is gone up with a shout, the LORD with the sound of a trumpet.
6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn. Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!
Sing praises to God, sing praises: sing praises unto our King, sing praises.
7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé, ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!
For God is the King of all the earth: sing ye praises with understanding.
8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí; Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.
God reigneth over the nations: God sitteth upon his holy throne.
9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni, òun ni ó ga jùlọ.
The princes of the peoples are gathered together [to be] the people of the God of Abraham: for the shields of the earth belong unto God; he is greatly exalted.

< Psalms 47 >