< Psalms 46 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
ʼElohim es nuestro Refugio y Fortaleza, Un auxilio muy presente en la tribulación.
2 Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí, tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
Por tanto, no temeremos aunque la tierra sea removida, Y las montañas se traspasen al corazón del mar,
3 Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. (Sela)
Aunque bramen y espumen sus aguas, Y tiemblen las montañas a causa de su ímpetu. (Selah)
4 Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn, ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
Hay un río cuyas corrientes alegran la ciudad de ʼElohim, El Santuario, morada del ʼElyón.
5 Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀: Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
ʼElohim está en medio de ella. No será conmovida. ʼElohim la ayudará al clarear la mañana.
6 Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú, ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
Braman las naciones, Se tambalean los reinos. Él emite su voz. Se derrite la tierra.
7 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa, Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
Yavé de las huestes está con nosotros. Nuestro Refugio es el ʼElohim de Jacob. (Selah)
8 Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
Vengan y miren las obras de Yavé, Quien causó asolamientos en la tierra,
9 O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
Quien hace cesar las guerras hasta el fin de la tierra, Quien quiebra el arco, rompe la lanza Y quema los carruajes en el fuego.
10 Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run. A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè, a ó gbé mi ga ní ayé.
Estén quietos y reconozcan que Yo soy ʼElohim. Seré exaltado entre las naciones. Seré enaltecido en la tierra.
11 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa; Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.
Yavé de las huestes está con nosotros. Nuestra Fortaleza es el ʼElohim de Jacob. (Selah)

< Psalms 46 >