< Psalms 46 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
Przewodnikowi chóru dla synów Korego. Pieśń na Alamot. Bóg [jest] naszą ucieczką i siłą, najpewniejszą pomocą w utrapieniu.
2 Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí, tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
Dlatego nie będziemy się bać, choćby się poruszyła ziemia, choćby się przeniosły góry w sam środek morza;
3 Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. (Sela)
Choćby huczały i burzyły się jego wody i zatrzęsły się góry od jego nawałnicy. (Sela)
4 Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn, ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
[Jest] rzeka, której strumienie rozweselają miasto Boże, [miejsce] święte przybytków Najwyższego.
5 Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀: Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
Bóg [jest] pośrodku niego, nie będzie zachwiane; Bóg je wspomoże zaraz o świcie.
6 Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú, ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
Wzburzyły się narody, zachwiały się królestwa, on wydał swój głos i rozpłynęła się ziemia.
7 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa, Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
PAN zastępów [jest] z nami; Bóg Jakuba [jest] naszą twierdzą. (Sela)
8 Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
Chodźcie, zobaczcie dzieła PANA, jakie spustoszenia uczynił na ziemi.
9 O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
On kładzie kres wojnom aż po krańce ziemi, kruszy łuki i łamie włócznie, a rydwany pali ogniem.
10 Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run. A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè, a ó gbé mi ga ní ayé.
Uspokójcie się i uznajcie, że ja jestem Bogiem; będę wywyższony wśród narodów, będę wywyższony na ziemi.
11 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa; Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.
PAN zastępów [jest] z nami, Bóg Jakuba [jest] naszą twierdzą. (Sela)

< Psalms 46 >