< Psalms 46 >
1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
God is our refuge and strength, a very present help in trouble.
2 Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí, tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
Therefore will not we fear, though the earth be removed, and though the mountains be carried into the middle of the sea;
3 Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. (Sela)
Though the waters thereof roar and be troubled, though the mountains shake with the swelling thereof. (Selah)
4 Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn, ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
There is a river, the streams whereof shall make glad the city of God, the holy place of the tabernacles of the most High.
5 Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀: Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
God is in the middle of her; she shall not be moved: God shall help her, and that right early.
6 Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú, ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
The heathen raged, the kingdoms were moved: he uttered his voice, the earth melted.
7 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa, Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
The LORD of hosts is with us; the God of Jacob is our refuge. (Selah)
8 Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
Come, behold the works of the LORD, what desolations he has made in the earth.
9 O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
He makes wars to cease to the end of the earth; he breaks the bow, and cuts the spear in sunder; he burns the chariot in the fire.
10 Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run. A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè, a ó gbé mi ga ní ayé.
Be still, and know that I am God: I will be exalted among the heathen, I will be exalted in the earth.
11 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa; Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.
The LORD of hosts is with us; the God of Jacob is our refuge. (Selah)