< Psalms 46 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Gẹ́gẹ́ bí ti alamoti. Orin. Ọlọ́run ni ààbò àti agbára wa ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ní ìgbà ìpọ́njú.
Kathutkung: Korah capanaw Cathut teh ka kânguenae hoi ka thaonae doeh. Runae tueng navah kabawmkung kahnai poung e doeh.
2 Nítorí náà àwa kì yóò bẹ̀rù, bí a tilẹ̀ ṣí ayé ní ìdí, tí òkè sì ṣubú sínú Òkun.
Hatdawkvah, talai heh kampuen niteh, monnaw teh talî dawk ka bawt nakunghai, ka taket mahoeh.
3 Tí omi rẹ̀ tilẹ̀ ń hó tí ó sì ń mì tí àwọn òkè ńlá tilẹ̀ ń mì pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀. (Sela)
Tuinaw teh hramki laihoi ka phuen nakunghai, tuicapa ni mon totouh ka thaw nakunghai, ka taket mahoeh.
4 Odò ńlá kan wà tí ṣíṣàn rẹ̀ mú inú ìlú Ọlọ́run dùn, ibi mímọ́, níbi ti Ọ̀gá-ògo ń gbé.
Palang buet touh ao teh, a cakang teh Cathut khopui, Lathueng Poung onae koe totouh, ka konawmsakkung lah ao.
5 Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀, kò ní yẹ̀: Ọlọ́run yóò ràn án lọ́wọ́ ní kùtùkùtù òwúrọ̀.
Cathut teh a thung vah ao teh, kâhuen mahoeh. Khodai toteh Cathut ni a kabawp han.
6 Àwọn orílẹ̀-èdè ń bínú, àwọn ilẹ̀ ọba ṣubú, ó gbé ohun rẹ̀ sókè, ayé yọ̀.
Miphun pueng teh a hramki awh. Uknae pueng teh a kâhuet. Ahni ni a lawk a tho boteh, talai teh a kamyawt.
7 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa, Ọlọ́run Jakọbu ni ààbò wa.
Ransahu BAWIPA teh, maimouh koe ao teh, Jakop Cathut teh kânguenae doeh.
8 Ẹ wá wo iṣẹ́ Olúwa irú ahoro tí ó ṣe ní ayé.
Tho awh haw, BAWIPA ni a sak e naw hoi talai van e hno a raphoe e naw pueng hah khenhaw.
9 O mú ọ̀tẹ̀ tán de òpin ilẹ̀ ayé ó ṣẹ́ ọrun, ó sì gé ọ̀kọ̀ sí méjì ó fi kẹ̀kẹ́ ogun jóná.
Ama ni tarantuknae hah talai pout totouh a roum sak teh, licung hah a khoe. Tahroe hah a tâtueng teh, lengnaw hah hmai hoi koung a sawi.
10 Ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ sì mọ̀ pé èmi ní Ọlọ́run. A ó gbé mi ga nínú àwọn orílẹ̀-èdè, a ó gbé mi ga ní ayé.
Duem awm awh nateh, Cathut lah ka o e heh panuek awh. Miphunnaw koe tawm lah ka o vaiteh, talai van vah tawm lah ka o han.
11 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú wa; Ọlọ́run Jakọbu sì ni ààbò wa.
Ransahu BAWIPA teh, maimouh koe ao. Jakop Cathut teh kânguenae doeh,

< Psalms 46 >