< Psalms 45 >

1 Fún adarí orin. Tí ohun orin “Lílì.” Ti orin àwọn ọmọ Kora. Maskili. Orin ìgbéyàwó. Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.
Przewodnikowi chóru, na Szoszanim dla synów Korego. Psalm pouczający. Pieśń miłosna. Wezbrało moje serce dobrym słowem; dzieła, które wypowiadam, dotyczą króla; mój język będzie jak pióro biegłego pisarza.
2 Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ: a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè: nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.
Ty jesteś najpiękniejszym z synów ludzkich; wdzięk rozlał się na twoich wargach, dlatego Bóg pobłogosławił cię na wieki.
3 Gba idà rẹ mọ́ ìhà rẹ, ìwọ alágbára jùlọ wọ ara rẹ ní ògo àti ọláńlá.
Przypasz do biodra swój miecz, mocarzu, w swej chwale i majestacie.
4 Nínú ọláńlá rẹ, máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́, ìwà tútù àti òtítọ́; jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ohun ẹ̀rù.
A w swym dostojeństwie wyrusz szczęśliwie ze słowem prawdy, łagodności i sprawiedliwości, a twoja prawica dokona strasznych rzeczy.
5 Jẹ́ kí ọfà mímú rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
Twoje ostre strzały, [od których] upadają narody pod twoje stopy, [przenikają] serce wrogów króla.
6 Ọlọ́run láé, àti láéláé ni ìtẹ́ rẹ, ọ̀pá aládé ìjọba rẹ, ọ̀pá aládé òtítọ́ ni.
Twój tron, o Boże, na wieki wieków, berłem sprawiedliwości [jest] berło twego królestwa.
7 Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run rẹ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ, nípa fífi àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́.
Miłujesz sprawiedliwość, a nienawidzisz nieprawości, dlatego namaścił cię, o Boże, twój Bóg olejkiem radości bardziej niż twoich towarzyszy.
8 Gbogbo aṣọ rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjìá àti aloe àti kasia; láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú rẹ̀ dùn.
Wszystkie twoje szaty [pachną] mirrą, aloesem [i] kasją, [gdy wychodzisz] z pałaców z kości słoniowej, z których cię rozweselają.
9 Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba wà nínú àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró nínú wúrà Ofiri.
Córki królewskie są wśród twoich czcigodnych [kobiet], królowa w złocie z Ofiru stoi po twojej prawicy.
10 Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí rẹ sí mi gbàgbé àwọn ènìyàn rẹ àti ilé baba rẹ.
Posłuchaj, córko, spójrz i nakłoń ucha, zapomnij o swoim narodzie i o domu swojego ojca;
11 Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà rẹ gidigidi nítorí òun ni olúwa rẹ kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.
A król zapragnie twojego piękna, bo on jest twoim Panem; oddaj mu pokłon.
12 Ọmọbìnrin ọba Tire yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojúrere rẹ̀.
Także córka Tyru przyjdzie z darami, najbogatsi z narodów będą zabiegać o twą przychylność.
13 Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárín ilé rẹ̀, iṣẹ́ wúrà ọnà abẹ́rẹ́ ní aṣọ rẹ̀.
Córka królewska jest pełna chwały w [swej] komnacie, a jej szaty złotem tkane.
14 Nínú aṣọ olówó iyebíye ni a mú un tọ́ ọba wá, àwọn wúńdíá ẹgbẹ́ rẹ̀ tẹ̀lé e, wọ́n sí mú un tọ̀ ọ́ wá.
W szacie haftowanej będą ją wieść do króla, za nią dziewice, jej towarzyszki, przyprowadzą do ciebie.
15 Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn wọ́n sì wọ ààfin ọba.
Wiodą [je] z weselem i z radością i wejdą do królewskiego pałacu.
16 Ọmọ rẹ̀ ni yóò gba ipò baba rẹ̀ ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.
Miejsce twoich ojców zajmą twoi synowie, których ustanowisz książętami po całej ziemi.
17 Èmí yóò máa rántí orúkọ rẹ̀ ní ìran gbogbo, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.
Upamiętnię twoje imię po wszystkie pokolenia; dlatego narody będą cię wysławiać na wieki wieków.

< Psalms 45 >