< Psalms 45 >

1 Fún adarí orin. Tí ohun orin “Lílì.” Ti orin àwọn ọmọ Kora. Maskili. Orin ìgbéyàwó. Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.
To the Chief Musician. On Shoshannim. For the Sons of Korah. A Psalm of Instruction. A Song of Love. Overflowed hath my heart, with an excellent theme, I will recite my poem concerning the king, Be, my tongue, [like] the pen of a scribe who is skilled.
2 Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ: a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè: nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.
Most beautiful thou art, beyond the sons of men, Graciousness hath been poured forth by thy lips, For this cause, hath God blessed thee, to times age-abiding.
3 Gba idà rẹ mọ́ ìhà rẹ, ìwọ alágbára jùlọ wọ ara rẹ ní ògo àti ọláńlá.
Gird thy sword upon thy thigh, O mighty one, [’Tis] thine honour and thy majesty;
4 Nínú ọláńlá rẹ, máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́, ìwà tútù àti òtítọ́; jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ohun ẹ̀rù.
And, [in] thy majesty, be successful! ride forth! on behalf of faithfulness, and humility—righteousness, And let thine own right hand show thee wonderful things.
5 Jẹ́ kí ọfà mímú rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
Thine arrows, are sharp—Peoples, under thee, fall! In the heart of the foes of the king.
6 Ọlọ́run láé, àti láéláé ni ìtẹ́ rẹ, ọ̀pá aládé ìjọba rẹ, ọ̀pá aládé òtítọ́ ni.
Thy throne, O God, is to times age-abiding and beyond, A sceptre of equity, is the sceptre of thy kingdom.
7 Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run rẹ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ, nípa fífi àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́.
Thou hast loved righteousness, and hated lawlessness, —For this cause, hath God, thine own God, anointed thee, With the oil of gladness, beyond thy partners.
8 Gbogbo aṣọ rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjìá àti aloe àti kasia; láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú rẹ̀ dùn.
Myrrh and aloes, cassias, all thy garments, —Out of the palaces of ivory, the tones of strings, have rejoiced thee.
9 Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba wà nínú àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró nínú wúrà Ofiri.
Daughters of kings, are among thine honourable women, Stationed is the bride at thy right hand, in gold of Ophir.
10 Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí rẹ sí mi gbàgbé àwọn ènìyàn rẹ àti ilé baba rẹ.
Hearken, O daughter, and observe, Incline also thine ear, Forget, then, thine own people, And the house of thy father;
11 Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà rẹ gidigidi nítorí òun ni olúwa rẹ kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.
When the king shall desire thy beauty, Surely, he, is thy lord, then bow down to him.
12 Ọmọbìnrin ọba Tire yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojúrere rẹ̀.
Also, the daughter of Tyre, [cometh in] with a present! Thy face, shall the rich of the people appease.
13 Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárín ilé rẹ̀, iṣẹ́ wúrà ọnà abẹ́rẹ́ ní aṣọ rẹ̀.
All glorious—the daughter of a king [sitteth] within, Brocades, wrought with gold, [are] her clothing!
14 Nínú aṣọ olówó iyebíye ni a mú un tọ́ ọba wá, àwọn wúńdíá ẹgbẹ́ rẹ̀ tẹ̀lé e, wọ́n sí mú un tọ̀ ọ́ wá.
In embroidered raiment, shall she be brought unto the king—The virgins that follow her, her companions, are to be conducted unto thee:
15 Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn wọ́n sì wọ ààfin ọba.
They shall be brought, with rejoicings and exultation, —They shall enter into the palace of the king!
16 Ọmọ rẹ̀ ni yóò gba ipò baba rẹ̀ ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.
Instead of thy fathers, be thy sons, Thou shalt make them rulers in all the earth.
17 Èmí yóò máa rántí orúkọ rẹ̀ ní ìran gbogbo, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.
I will keep in remembrance thy Name, through each succeeding generation, For this cause, peoples, shall praise thee, to times age-abiding and beyond.

< Psalms 45 >