< Psalms 44 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili. À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run; àwọn baba wa tí sọ fún wa ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn, ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.
برای رهبر سرایندگان. قصیدۀ پسران قورَح. ای خدا، ما به گوشهای خود شنیده‌ایم و اجدادمان برای ما تعریف کرده‌اند که تو در گذشته چه کارهای شگفت‌انگیزی برای آنان انجام داده‌ای.
2 Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde, Ìwọ sì gbin àwọn baba wa; ìwọ run àwọn ènìyàn náà Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.
تو به دست خود قومهای بت‌پرست را از این سرزمین بیرون راندی و اجداد ما را به جای آنها مستقر نمودی. قومهای خدانشناس را از بین بردی، اما بنی‌اسرائیل را در سرزمین موعود تثبیت نمودی.
3 Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ; àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.
قوم تو به زور شمشیر این سرزمین را تسخیر نکردند و به قدرت بازوی خویش نجات نیافتند، بلکه قدرت و توانایی تو و اطمینان به حضور تو ایشان را رهانید، زیرا از ایشان خرسند بودی.
4 Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi, ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.
ای خدا، تو پادشاه من هستی؛ اکنون نیز قوم خود اسرائیل را پیروز گردان.
5 Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú; nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀,
ما با کمک تو دشمنان خود را شکست خواهیم داد و به نام تو کسانی را که بر ضد ما برخاسته‌اند، پایمال خواهیم کرد.
6 èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi, idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,
امید من به تیر و کمانم نیست، و نه به شمشیرم که مرا نجات دهد،
7 ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa, ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.
زیرا این تو بودی که ما را از دست دشمنان نجات دادی، و آنانی را که از ما متنفر بودند شکست دادی.
8 Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́, àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. (Sela)
برای همیشه تو را ستایش خواهیم کرد، و تا ابد از تو سپاسگزار خواهیم بود.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá, Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.
اما اکنون تو ما را دور انداخته‌ای و رسوا ساخته‌ای؛ دیگر لشکرهای ما را در جنگ کمک نمی‌کنی.
10 Ìwọ ti bá wa jà, ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa, àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa, wọ́n sì fi ipá gba oko wa.
تو ما را در مقابل دشمنان شکست داده‌ای و آنها اکنون ما را غارت می‌کنند.
11 Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn, Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.
ما را همچون گوسفندان به کشتارگاه فرستاده‌ای و در میان قومهای خدانشناس پراکنده ساخته‌ای.
12 Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré, Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.
تو قوم برگزیده‌ات را ارزان فروخته‌ای و از فروش آنها سودی نبرده‌ای.
13 Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa, ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.
ما را نزد همسایگان خوار ساخته‌ای و ما مورد تمسخر و توهین اطرافیان قرار گرفته‌ایم.
14 Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.
ما را در میان قومهای خدانشناس انگشت‌نما ساخته‌ای و آنها ما را به باد ریشخند گرفته‌اند.
15 Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́, ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,
از تحقیر دائمی آنها گریزی نیست؛ صورتهای ما از شرم پوشیده شده است.
16 nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.
از هر سو دشنامهای مخالفان به گوش ما می‌رسد و در برابر خود دشمنان انتقامجو را می‌بینیم.
17 Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa, síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.
این همه بر ما واقع شده است، ولی تو را فراموش نکرده‌ایم و پیمانی را که با ما بسته‌ای نشکسته‌ایم.
18 Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
نسبت به تو دلسرد نشده‌ایم و از راه تو منحرف نگشته‌ایم.
19 Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá, ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú, tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.
با وجود این، تو ما را در میان حیوانات وحشی رها نموده‌ای و با مرگ روبرو ساخته‌ای.
20 Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.
اگر ما نام خدای خود را فراموش می‌کردیم و دستهای خود را به سوی بتها دراز می‌کردیم،
21 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?
آیا خدا که اسرار دل هر کس را می‌داند، این را نمی‌دانست؟
22 Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́ a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.
تو می‌دانی که ما به خاطر تو هر روز با مرگ روبرو می‌شویم و با ما همچون گوسفندانی که باید قربانی شوند رفتار می‌کنند.
23 Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn? Dìde fúnra rẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.
ای خداوند، بیدار شو! چرا خوابیده‌ای؟ بیدار شو و ما را تا ابد دور نیانداز!
24 Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́ tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?
چرا روی خود را از ما برمی‌گردانی و ذلت و خواری ما را نادیده می‌گیری؟
25 Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku; ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.
اینک به خاک افتاده و مغلوب شده‌ایم.
26 Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́; rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
برخیز و به کمک ما بشتاب و ما را نجات ده زیرا تو سراسر، رحمت و محبتی!

< Psalms 44 >