< Psalms 44 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili. À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run; àwọn baba wa tí sọ fún wa ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn, ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.
Au maître-chantre. — Hymne des enfants de Coré. Dieu, nous avons entendu de nos oreilles, Nos pères nous ont raconté L'oeuvre que tu as faite de leur temps, Aux jours d'autrefois.
2 Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde, Ìwọ sì gbin àwọn baba wa; ìwọ run àwọn ènìyàn náà Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.
De ta main tu les as établis, en dépossédant les nations; Tu as détruit des peuples pour leur faire une place.
3 Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ; àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.
Car ce n'est pas leur épée qui leur a conquis le pays; Ce n'est pas leur bras qui les a sauvés: C'est ta main droite, c'est ton bras, C'est la lumière de ta face. Parce que tu leur étais favorable!
4 Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi, ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.
Dieu, toi qui es mon roi. Donne à Jacob la victoire!
5 Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú; nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀,
Par toi nous repousserons nos ennemis; En ton nom nous écraserons nos adversaires.
6 èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi, idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,
Car ce n'est pas en mon arc que je mets ma confiance; Ce n'est pas mon épée qui me sauvera.
7 ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa, ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.
C'est toi qui nous as délivrés de nos oppresseurs. Et qui as couvert de honte nos ennemis.
8 Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́, àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. (Sela)
C'est en Dieu que nous nous glorifions chaque jour; Nous célébrerons son nom éternellement. (Pause)
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá, Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.
Cependant, tu nous as rejetés et couverts d'opprobre, Et tu ne sors plus avec nos armées.
10 Ìwọ ti bá wa jà, ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa, àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa, wọ́n sì fi ipá gba oko wa.
Tu nous fais reculer devant l'oppresseur. Et nos ennemis se partagent nos dépouilles.
11 Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn, Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.
Tu nous livres comme des brebis à dévorer; Tu nous as dispersés parmi les nations.
12 Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré, Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.
Tu vends ton peuple pour rien. Et tu le mets à vil prix.
13 Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa, ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.
Tu fais de nous un objet d'opprobre pour nos voisins; Nous sommes la risée, le jouet de ceux qui nous entourent.
14 Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.
Oui, tu fais de nous la fable des nations; En nous voyant, les peuples hochent la tête.
15 Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́, ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,
La honte m'accable tous les jours, Et la confusion couvre mon visage,
16 nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.
A la voix de celui qui m'insulte et m'outrage, Sous les regards de mon ennemi, De celui qui s'acharne à ma perte.
17 Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa, síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.
Tous ces malheurs nous sont arrivés. Cependant nous ne t'avions pas oublié. Nous n'avions pas violé ton alliance.
18 Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
Notre coeur ne s'était pas détourné de toi; Nos pas ne s'étaient point écartés de ton sentier.
19 Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá, ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú, tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.
Et pourtant, tu nous as refoulés parmi les chacals; Tu nous as couverts de l'ombre de la mort.
20 Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.
Si nous eussions oublié le nom de notre Dieu, Si nous eussions étendu nos mains vers un Dieu étranger,
21 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?
Dieu n'en serait-il pas informé, Lui qui connaît les secrets du coeur?
22 Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́ a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.
Mais c'est à cause de toi Que nous sommes sans cesse livrés à la mort. Et traités comme des brebis destinées à la boucherie!
23 Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn? Dìde fúnra rẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.
Réveille-toi! Pourquoi dors-tu, Seigneur? Lève-toi, ne nous rejette pas pour toujours!
24 Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́ tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?
Pourquoi caches-tu ta face? Pourquoi oublies-tu notre misère et notre détresse?
25 Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku; ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.
Car notre âme est abattue dans la poussière; Notre corps reste attaché à la terre.
26 Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́; rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
Lève-toi, viens à notre aide, Et délivre-nous, à cause de ta bonté!

< Psalms 44 >