< Psalms 42 >

1 Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora. Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
Au maître-chantre. — Hymne des enfants de Goré. Comme un cerf brame après les eaux courantes, Ainsi mon âme soupire après toi, ô Dieu!
2 Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè. Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
Mon âme a soif de Dieu, du Dieu vivant. Quand entrerai-je et me présenterai-je devant sa face?
3 Oúnjẹ mi ni omijé mi ní ọ̀sán àti ní òru, nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé, “Ọlọ́run rẹ dà?”
Les larmes sont jour et nuit ma nourriture, Depuis qu'on me dit sans cesse: «Où est ton Dieu?»
4 Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí, èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi: èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ, èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
Je me souviens — et mon coeur se brise à ce souvenir! — Que je marchais avec la foule, Et m'avançais à sa tête jusqu'à la maison de Dieu, Au milieu des cris de joie et de louange D'une multitude en fête.
5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín, Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Pourquoi t'abats-tu, mon âme, et pourquoi frémis-tu en moi? Espère en Dieu; car je le célébrerai encore: Il est mon salut et mon Dieu!
6 Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi: nítorí náà, èmi ó rántí rẹ láti ilẹ̀ Jordani wá, láti Hermoni láti òkè Mibsari.
Mon âme est abattue en moi, Parce que je pense à toi, ô Dieu, dans le pays du Jourdain, Et dans les montagnes de l'Hermon et de Mitséar.
7 Ibú omi ń pe ibú omi nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀ gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀ bò mí mọ́lẹ̀.
La vague appelle la vague, quand mugit la tempête; Tous les flots, tous les torrents ont passé sur moi.
8 Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀, àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
Pendant le jour, l'Éternel répandait sur moi sa grâce. Et la nuit sa louange était sur ma bouche. Je prie le Dieu qui est ma vie;
9 Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi, “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi? Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́, nítorí ìnilára ọ̀tá?”
Je dis à Dieu, mon rocher: «Pourquoi m'as-tu oublié?» Pourquoi marcherais-je en vêtements de deuil, Sous l'oppression de l'ennemi?
10 Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí, bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́. “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
Je sens mes os se briser, quand mes oppresseurs m'outragent, En me disant chaque jour: «Où est ton Dieu?»
11 Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Pourquoi t'abats-tu, mon âme, et pourquoi frémis-tu en moi? Espère en Dieu; car je le célébrerai encore: Il est mon salut et mon Dieu!

< Psalms 42 >