< Psalms 42 >
1 Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora. Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
Koran lasten opetus, edelläveisaajalle. Niinkuin peura himoitsee tuoretta vettä, niin minun sieluni himoitsee sinua, Jumala.
2 Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè. Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
Minun sieluni janoo Jumalaa, elävää Jumalaa: koska minä tulen Jumalan kasvoja näkemään?
3 Oúnjẹ mi ni omijé mi ní ọ̀sán àti ní òru, nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé, “Ọlọ́run rẹ dà?”
Minun kyyneleeni ovat minun ruokani päivällä ja yöllä, että joka päivä minulle sanotaan: kussa nyt on Jumalas?
4 Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí, èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi: èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ, èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
Koska minä näitä muistelen, niin minä vuodatan ulos sydämeni itsessäni; sillä minä menisin mielelläni joukon kanssa, ja vaeltaisin heidän kanssansa Jumalan huoneeseen: ihastuksella ja kiitoksella joukon seassa, jotka juhlaa pitävät.
5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín, Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Mitäs murehdit, sieluni, ja olet niin levotoin minussa? Turvaa Jumalaan; sillä minä vielä nytkin häntä kiitän, että hän minua auttaa kasvoillansa.
6 Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi: nítorí náà, èmi ó rántí rẹ láti ilẹ̀ Jordani wá, láti Hermoni láti òkè Mibsari.
Minun Jumalani! sieluni on murheissansa minussa; sentähden minä muistan sinua Jordanin ja Hermonin maalla, sillä vähällä vuorella.
7 Ibú omi ń pe ibú omi nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀ gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀ bò mí mọ́lẹ̀.
Sinun virtas pauhaavat kovin, niin että yksi syvyys pauhaa tässä ja toinen syvyys siellä: kaikki sinun vesilainees ja aaltos käyvät minun ylitseni.
8 Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀, àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
Päivällä on Herra luvannut hyvyytensä, ja yöllä minä hänelle veisaan, ja rukoilen elämäni Jumalaa.
9 Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi, “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi? Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́, nítorí ìnilára ọ̀tá?”
Minä sanon Jumalalle minun kalliolleni: miksi sinä olet minun unohtanut? miksi minä käyn niin murheissani, koska minun viholliseni minua ahdistaa?
10 Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí, bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́. “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
Se on niinkuin murha minun luissani, että minun viholliseni häpäisevät minua, koska he jokapäivä sanovat minulle: kussa nyt on Jumalas?
11 Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Mitäs murehdit, sieluni, ja olet minussa niin levotoin? Turvaa Jumalaan; sillä minä vielä nytkin häntä kiitän, että hän on minun kasvoini apu ja minun Jumalani.