< Psalms 41 >
1 Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
Фериче де чел че ынгрижеште де чел сэрак, кэч ын зиуа ненорочирий Домнул ыл избэвеште;
2 Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Домнул ыл пэзеште ши-л цине ын вяцэ. Ел есте феричит пе пэмынт ши ну-л лашь ла бунул плак ал врэжмашилор луй.
3 Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
Домнул ыл сприжинэ кынд есте пе патул де суферинцэ: ый ушурезь дурериле ын тоате болиле луй.
4 Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
Еу зик: „Доамне, ай милэ де мине! Виндекэ-мь суфлетул, кэч ам пэкэтуит ымпотрива Та!”
5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
Врэжмаший мей зик ку рэутате деспре мине: „Кынд ва мури? Кынд ый ва пери нумеле?”
6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
Дакэ вине чинева сэ мэ вадэ, ворбеште неадевэрурь, стрынӂе темеюрь ка сэ мэ ворбяскэ де рэу; ши кынд плякэ, мэ ворбеште де рэу пе афарэ.
7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
Тоць врэжмаший мей шоптеск ынтре ей ымпотрива мя ши кред кэ ненорочиря мя ымь ва адуче пеиря.
8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
„Есте атинс рэу де тот”, зик ей, „ятэ-л кулкат, н-аре сэ се май скоале!”
9 Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
Кяр ши ачела ку каре трэям ын паче, ын каре ымь пуням ынкредеря ши каре мынка дин пыня мя, ридикэ ши ел кэлкыюл ымпотрива мя.
10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
Дар Ту, Доамне, ай милэ де мине ши ридикэ-мэ, ка сэ ле рэсплэтеск кум ли се кувине!
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
Прин ачаста вой куноаште кэ мэ юбешть, дакэ ну мэ ва бируи врэжмашул меу.
12 Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
Ту м-ай сприжинит дин причина неприхэнирий меле ши м-ай ашезат пе вечие ынаинтя Та.
13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.
Бинекувынтат сэ фие Домнул Думнезеул луй Исраел, дин вешничие ын вешничие! Амин! Амин!