< Psalms 41 >

1 Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
למנצח מזמור לדוד אשרי משכיל אל דל ביום רעה ימלטהו יהוה׃
2 Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
יהוה ישמרהו ויחיהו יאשר בארץ ואל תתנהו בנפש איביו׃
3 Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
יהוה יסעדנו על ערש דוי כל משכבו הפכת בחליו׃
4 Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
אני אמרתי יהוה חנני רפאה נפשי כי חטאתי לך׃
5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
אויבי יאמרו רע לי מתי ימות ואבד שמו׃
6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
ואם בא לראות שוא ידבר לבו יקבץ און לו יצא לחוץ ידבר׃
7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
יחד עלי יתלחשו כל שנאי עלי יחשבו רעה לי׃
8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
דבר בליעל יצוק בו ואשר שכב לא יוסיף לקום׃
9 Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
גם איש שלומי אשר בטחתי בו אוכל לחמי הגדיל עלי עקב׃
10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
ואתה יהוה חנני והקימני ואשלמה להם׃
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
בזאת ידעתי כי חפצת בי כי לא יריע איבי עלי׃
12 Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
ואני בתמי תמכת בי ותציבני לפניך לעולם׃
13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.
ברוך יהוה אלהי ישראל מהעולם ועד העולם אמן ואמן׃

< Psalms 41 >