< Psalms 41 >

1 Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
Pour le chef musicien. Un psaume de David. Béni soit celui qui considère les pauvres. Yahvé le délivrera au jour du malheur.
2 Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
L'Éternel le protégera et le fera vivre. Il sera béni sur la terre, et il ne le livrera pas à la volonté de ses ennemis.
3 Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
Yahvé le soutiendra sur son lit de malade, et le faire sortir de son lit de maladie.
4 Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
J'ai dit: « Yahvé, aie pitié de moi! Guéris-moi, car j'ai péché contre toi. »
5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
Mes ennemis disent du mal de moi: « Quand mourra-t-il, et son nom périra-t-il? »
6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
S'il vient me voir, il dit des mensonges. Son cœur rassemble l'iniquité à lui. Quand il va à l'étranger, il le raconte.
7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
Tous ceux qui me haïssent murmurent ensemble contre moi. Ils imaginent le pire pour moi.
8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
« Une mauvaise maladie », disent-ils, « l'a affligé ». Maintenant qu'il est couché, il ne se relèvera plus. »
9 Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
Oui, mon ami familier, en qui j'avais confiance, qui ont mangé du pain avec moi, a levé son talon contre moi.
10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
Mais toi, Yahvé, aie pitié de moi, et relève-moi, pour que je leur rende la pareille.
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
Je sais par là que tu te plais en moi, car mon ennemi ne triomphe pas de moi.
12 Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
Quant à moi, tu me soutiens dans mon intégrité, et me mettre en ta présence pour toujours.
13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.
Bénisoit Yahvé, le Dieu d'Israël, de l'éternité et à l'éternité! Amen et amen.

< Psalms 41 >