< Psalms 41 >

1 Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
Kuom jatend wer. Zaburi mar Daudi. Ngʼama paro joma ok nyal en jahawi; Jehova Nyasaye rese ka chandruok omake.
2 Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Jehova Nyasaye biro rite kendo biro miyo obed mangima; Jehova Nyasaye biro gwedhe e piny, kendo ok obi jwangʼe e lwet wasike.
3 Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
Jehova Nyasaye biro rite e kitandane mar tuo midekre kendo obiro miyo oa malo e kitandane ka ohewore.
4 Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
Ne awacho niya, “Yaye Jehova Nyasaye, kecha; changa, nikech aseketho e nyimi.”
5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
Wasika wuoyo kuoma ka chunygi rach koda, kagiwacho niya, “Obiro tho karangʼo mondo nyinge olal chuth?”
6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
Sa asaya ma ngʼato obiro nena, to owuondore ni owuoyo kuoma maber, to ei chunye to ofwambo weche, mondo okethgo nyinga eka oa odhi kendo okeyo wechego ne ji.
7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
Wasika duto kuodho wach kuoma kaachiel kaka ginyalo hinya, chunygi paro gik maricho mogik mondo ohinya, kagiwacho niya,
8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
“Tuo marach osekete piny; ok obi aa malo kama oninde.”
9 Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
Koda ka osiepna mane ageno kuome, ngʼat mane chiemo koda, bende osendhoga.
10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
To in, yaye Jehova Nyasaye, yie ikecha; chunga malo, mondo achulgi.
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
Angʼeyo ni chunyi mor koda, nimar jowasika ok loya.
12 Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
Itingʼa malo nikech timna makare kendo ichunga e nyimi nyaka chiengʼ.
13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.
Pak ne Jehova Nyasaye, ma Nyasach Israel, nyaka chiengʼ kendo nyaka chiengʼ.

< Psalms 41 >