< Psalms 41 >

1 Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
Přednímu zpěváku, žalm Davidův. Blahoslavený, kdož prozřetelný soud činí o chudém; v den zlý vysvobodí jej Hospodin.
2 Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Hospodin ho ostřeže, a obživí jej; blažený bude na zemi, aniž ho vydá líbosti nepřátel jeho.
3 Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
Hospodin ho na ložci ve mdlobě posilí, všecko ležení jeho v nemoci jeho promění.
4 Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
Já řekl jsem: Hospodine, smiluj se nade mnou, uzdrav duši mou, nebo jsem tobě zhřešil.
5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
Nepřátelé moji mluvili zle o mně, řkouce: Skoro-liž umřel, a zahyne jméno jeho?
6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
A jestliže kdo z nich přichází, aby mne navštívil, pochlebenství mluví; srdce jeho sbírá sobě nepravost, a vyjda ven, roznáší ji.
7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
Sšeptávají se spolu proti mně všickni, kteříž mne nenávidí, a přičítají mi zlé věci, říkajíce:
8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
Pomsta pro nešlechetnost přichytila se ho, a kdyžtě se složil nepovstaneť zase.
9 Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
Také i ten, s nímž jsem byl v přátelství, jemuž jsem se dověřoval, a kterýž jídal chléb můj, pozdvihl paty proti mně.
10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
Ale ty, Hospodine, smiluj se nade mnou, a pozdvihni mne, a odplatím jim;
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
Abych odtud poznal, že mne sobě libuješ, když by se neradoval nade mnou nepřítel můj.
12 Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
Mne pak v upřímnosti mé zachováš, a postavíš před oblíčejem svým na věky.
13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.
Požehnaný Hospodin Bůh Izraelský, od věků až na věky, Amen i Amen.

< Psalms 41 >