< Psalms 41 >

1 Fún adarí orin. Saamu Dafidi. Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ń ro ti aláìní: Olúwa yóò gbà á ní ìgbà ìpọ́njú.
Nowa dunu ilia da hame gagui dunuma asigiwane dawa: digisawane esala, ilia da hahawane gala. Bidi hamosu da ilima doaga: sea, Hina Gode da ili fidimu.
2 Olúwa yóò dáàbò bò ó yóò sì pa ọkàn rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún un ní orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀.
Hina Gode da ili gaga: mu, amola ili esaloma: ne fidimu. E da ili soge ganodini hahawane esaloma: mu. E da ilima ha lai dunu ilima hasalima: ne hamedafa yolesimu.
3 Olúwa yóò gbà á lórí àkéte àìsàn rẹ̀ yóò sì mú un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn rẹ̀.
Ilia da oloi galea, Hina Gode da ili fidimu. E da ili bu uhinisimu.
4 Ní ti èmi, mo wí pé “Olúwa, ṣàánú fún mi; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.
Na da amane sia: i, “Hina Gode! Na da Dima fawane wadela: le hamoi! Be nama asigi gogolema: ne olofosu hou hamoma amola na uhinisima.
5 Àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ mi nínú àrankàn, pé, “Nígbà wo ni yóò kú, ti orúkọ rẹ̀ yóò sì run?”
Nama ha lai dunu ilia da na hou higale sia: sa. Ilia da na bogole, gogole dagoi ba: mu hanai gala.
6 Nígbàkígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kálẹ̀.
Dunu ilia da na oloi ba: la mabe amo da ogogole ba: la maha. Ilia da na hou olelemusa: baligidu sia: lalabalasa. Amasea, ilia da gadili asili, amo sia: soge huluane sisia: i laha.
7 Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọ́n ń gbìmọ̀ ibi sí,
Nama higa: i dunu huluane ilia da ilisu sadoga sia: daha. Ilia da ilia asigiga na da wadela: lesi dagoi dawa: lala.
8 wọ́n wí pé, “Ohun búburú ni ó dì mọ́ ọn ṣinṣin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́.”
Ilia da agoane sia: daha, “E da bogomusa: fawane oloi. E da ea golasu hamedafa bu yolesimu.”
9 Pàápàá, ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgísẹ̀ rẹ̀ sókè sí mi.
Na sama ni dogolegeidafa ani ha: i segele nasu, ea amolawane da ogobele halasa.
10 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.
Hina Gode! Nama asigima amola na oloi uhinisima! Amasea, na da na ha lai dunu ilima dabe imunu. Amasea, Di da nama hahawane gala, amo na da dawa: digimu.
11 Èmi mọ̀ pé inú rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.
Ilia da na hame hasalimu. Amasea, Di da nama hahawane gala, amo na da dawa: digimu. Bai na da moloidafa hou amo hamosa.
12 Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mímú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú rẹ títí láé.
Dia da na fidimu. Bai na da moloidafa hou amo hamosa. Dia da na Dia midadi fifi ahoanoma: ne hamomu.
13 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé.
Hina Gode, Isala: ili Gode, Ema nodone sia: ma! Ema wali amola eso huluane nodonanuma: ma! Ama! Ama!

< Psalms 41 >