< Psalms 40 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa; ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
Dawut yazghan küy: — Perwerdigargha telmürüp, küttüm, küttüm; U manga égilip peryadimni anglidi.
2 Ó fà mí yọ gòkè láti inú ihò ìparun, láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta, ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
U méni halaket orikidin, Shundaqla patqaq laydin tartiwaldi, Putlirimni uyultash üstige turghuzup, Qedemlirimni mustehkem qildi.
3 Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu, àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa. Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
U aghzimgha yéngi naxsha-munajatni, Yeni Xudayimizni medhiyileshlerni saldi; Nurghun xelq buni körüp, qorqidu, Hem Perwerdigargha tayinidu.
4 Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga, tàbí àwọn tí ó yapa lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
Tekebburlardin yardem izdimeydighan, Yalghanchiliqqa ézip ketmeydighan, Belki Perwerdigarni öz tayanchisi qilghan kishi bextliktur!
5 Olúwa Ọlọ́run mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe. Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa; ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ, tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn, wọ́n ju ohun tí ènìyàn le è kà lọ.
I Perwerdigar Xudayim, Séning biz üchün qilghan karametliring we oy-niyetliringni barghanséri köpeytip, san-sanaqsiz qilghansen, Kimmu ularni bir-birlep hésablap Özüngge [rehmet qayturup] bolalisun! Ularni sözlep bashtin-axir bayan qilay désem, Ularni sanap tügitish mumkin emes.
6 Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́, ìwọ ti ṣí mi ní etí. Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò béèrè.
Ne qurbanliq, ne ash hediyeler Séning telep-arzuyung emes, Biraq Sen manga [sezgür] qulaqlarni ata qilding; Ne köydürme qurbanliq, ne gunah qurbanliqini telep qilmiding;
7 Nígbà náà ni mo wí pé, “Èmi nìyí; nínú ìwé kíká ni a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
Shunga jawab berdimki — «Mana men keldim!» — dédim. Oram yazma desturda men toghruluq pütülgen: —
8 Mo ní inú dídùn láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ, ìwọ Ọlọ́run mi, òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
«Xudayim, Séning könglüngdiki iradeng méning xursenlikimdur; Séning Tewrat qanunung qelbimge pütüklüktur».
9 Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà láàrín àwùjọ ńlá; wò ó, èmi kò pa ètè mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀, ìwọ Olúwa.
Büyük jamaet arisida turup men heqqaniyliqni jakarlidim; Mana bularni özümde qilche élip qalghum yoqtur, I Perwerdigar, Özüng bilisen.
10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi; èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ. Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
Heqqaniyliqingni qelbimde yoshurup yürmidim; Wapadarliqingni we nijatliqingni jakarlidim; Özgermes muhebbiting we heqiqitingni büyük jamaetke héch yoshurmastin bayan qildim.
11 Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
I Perwerdigar, méhribanliqliringni mendin ayimighaysen; Özgermes muhebbiting we heqiqiting herdaim méni saqlighay!
12 Nítorí pé àìníye ibi ni ó yí mi káàkiri, ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi, títí tí èmi kò fi ríran mọ́; wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, àti wí pé àyà mí ti kùnà.
Chünki sansiz külpetler méni oriwaldi; Qebihliklirim méni bésiwélip, körelmeydighan boldum; Ular béshimdiki chéchimdin köp, Jasaritim tügiship ketti.
13 Jẹ́ kí ó wù ọ́, ìwọ Olúwa, láti gbà mí là; Olúwa, yára láti ràn mí lọ́wọ́.
Méni qutquzushni toghra tapqaysen, i Perwerdigar! I Perwerdigar, téz kélip, manga yardem qilghaysen!
14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì kí wọn kí ó sì dààmú; àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n, àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Méning hayatimgha chang salmaqchi bolghanlar biraqla yerge qaritilip reswa qilinsun; Méning ziyinimdin xursen bolghanlar keynige yandurulup shermende bolghay.
15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!” ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
Méni: — «Wah! Wah!» dep mesxire qilghanlar öz shermendilikidin alaqzade bolup ketsun!
16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ kí ó máa yọ̀ kí inú wọn sì máa dùn sí ọ; kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ kí o máa wí nígbà gbogbo pé, “Gbígbéga ni Olúwa!”
Biraq Séni izdigüchilerning hemmisi Sende shadlinip xushal bolghay! Nijatliqingni söygenler hemishe: «Perwerdigar ulughlansun» déyishkey!
17 Bí ó ṣe ti èmi ni, tálákà àti aláìní ni èmi, ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi àti ìgbàlà mi; má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́, ìwọ Ọlọ́run mi.
Men ézilgen hem yoqsul bolsammu, Biraq Reb yenila méni yad étidu; Sen méning Yardemchim, méning azad qilghuchim; I Xudayim, kéchikmey kelgeysen!