< Psalms 40 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa; ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
Thaburi ya Daudi Ndetereire Jehova o ngirĩrĩirie; nake agĩĩthikĩrĩria akĩigua kĩrĩro gĩakwa.
2 Ó fà mí yọ gòkè láti inú ihò ìparun, láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta, ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
Nĩ aandutire irima rĩa mũũro, thĩinĩ wa ndoro yarĩ ndenderũ, agĩkinyithia magũrũ makwa igũrũ rĩa rwaro rwa ihiga, na agĩtũma ndĩhaande wega.
3 Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu, àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa. Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Eekĩrire rwĩmbo rwerũ kanua-inĩ gakwa, rwĩmbo rwa kũgoocaga Ngai witũ naruo. Andũ aingĩ marĩonaga ũguo magetigĩra, nao makehoka Jehova.
4 Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga, tàbí àwọn tí ó yapa lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
Kũrathimwo nĩ mũndũ ũrĩa ũtuĩte atĩ arĩĩhokaga o Jehova, na nderĩgagĩrĩra andũ arĩa etĩĩi, o acio marũmagĩrĩra ngai cia maheeni.
5 Olúwa Ọlọ́run mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe. Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa; ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ, tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn, wọ́n ju ohun tí ènìyàn le è kà lọ.
Wee Jehova Ngai wakwa-rĩ, magegania marĩa wĩkĩte nĩ maingĩ. Maũndũ marĩa ũtũbangĩire gũtirĩ mũndũ ũngĩhota gũgũtaarĩria; korwo ndaaria heane ũhoro wamo-rĩ, mangĩkorwo marĩ maingĩ mũno kũmoiga.
6 Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́, ìwọ ti ṣí mi ní etí. Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò béèrè.
Wee-rĩ, ti magongona na maruta weriragĩria, no nĩũũheete matũ ma gũkũigua; maruta ma njino na maruta ma kũhoroheria mehia ti mo maakũbatairie.
7 Nígbà náà ni mo wí pé, “Èmi nìyí; nínú ìwé kíká ni a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
Ningĩ ngiuga atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha, nĩndooka, o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo ũhoro wakwa ibuku-inĩ rĩa gĩkũnjo.
8 Mo ní inú dídùn láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ, ìwọ Ọlọ́run mi, òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
Niĩ ndĩriragĩria gwĩka wendi waku, Wee Ngai wakwa; watho waku ũrĩ ngoro-inĩ yakwa.”
9 Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà láàrín àwùjọ ńlá; wò ó, èmi kò pa ètè mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀, ìwọ Olúwa.
Nyanagĩrĩra ũhoro wa ũthingu ndĩ kĩũngano-inĩ kĩnene; o ta ũrĩa ũũĩ, Wee Jehova, niĩ ndihingaga mĩromo yakwa.
10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi; èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ. Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
Niĩ ndihithagĩrĩra ũthingu waku ngoro-inĩ yakwa; njaragia ũhoro wa wĩhokeku na ũhonokio waku. Wendo waku na ũhoro waku wa ma ndirĩ ndacihitha kĩũngano kĩrĩa kĩnene.
11 Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
Wee Jehova-rĩ, ndũkagirĩrĩrie tha ciaku inginyĩrĩre; wendo waku na ũhoro waku wa ma irongitagĩra hĩndĩ ciothe.
12 Nítorí pé àìníye ibi ni ó yí mi káàkiri, ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi, títí tí èmi kò fi ríran mọ́; wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, àti wí pé àyà mí ti kùnà.
Nĩgũkorwo mathĩĩna matangĩtarĩka nĩmandigiicĩirie; mehia makwa nĩmanginyĩrĩire, ngaremwo nĩkuona. Maingĩhĩte gũkĩra njuĩrĩ cia mũtwe wakwa, na ngoro yakwa nĩyũrĩtwo nĩ hinya.
13 Jẹ́ kí ó wù ọ́, ìwọ Olúwa, láti gbà mí là; Olúwa, yára láti ràn mí lọ́wọ́.
Wee Jehova-rĩ, ĩtĩkĩra kũũhonokia, Wee Jehova-rĩ, ũka narua ũndeithie.
14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì kí wọn kí ó sì dààmú; àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n, àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Andũ arĩa othe mendaga kũnjũraga maroconorithio na manyiitwo nĩ kĩrigiicano; arĩa othe mendaga nyanangwo marocooka na thuutha maconokete.
15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!” ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
Andũ arĩa maathekagĩrĩra makiugaga atĩrĩ, “Haiya! Haiya!” Maroiyũrwo nĩ ihooru nĩ ũndũ wa thoni ciao.
16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ kí ó máa yọ̀ kí inú wọn sì máa dùn sí ọ; kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ kí o máa wí nígbà gbogbo pé, “Gbígbéga ni Olúwa!”
No arĩa makũrongoragia marokena na macanjamũke nĩ ũndũ waku; arĩa mendete ũhonokio waku marotũũra moigaga atĩrĩ, “Jehova arotũgĩrio!”
17 Bí ó ṣe ti èmi ni, tálákà àti aláìní ni èmi, ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi àti ìgbàlà mi; má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́, ìwọ Ọlọ́run mi.
No rĩrĩ, niĩ ndĩ mũthĩĩni na mũbatari; Mwathani arondirikana. Wee nĩwe ũteithio wakwa na mũndeithũri; Wee Ngai wakwa-rĩ, hiuha ũkĩndeithie.

< Psalms 40 >