< Psalms 40 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa; ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
Přednímu zpěváku, Davidův žalm. Žádostivě očekával jsem na Hospodina, i naklonil se ke mně, a vyslyšel mé volání.
2 Ó fà mí yọ gòkè láti inú ihò ìparun, láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta, ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
A vytáhl mne z čisterny hlučící, i z bláta bahnivého, a postavil na skále nohy mé, a kroky mé utvrdil.
3 Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu, àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa. Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
A tak vložil v ústa má píseň novou, chválu Bohu našemu, což když uhlédají mnozí, i báti se, i doufání skládati budou v Hospodinu.
4 Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga, tàbí àwọn tí ó yapa lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
Blahoslavený ten člověk, kterýž skládá v Hospodinu svou naději, a neohlédá se na pyšné, ani na ty, kteříž se ke lži uchylují.
5 Olúwa Ọlọ́run mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe. Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa; ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ, tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn, wọ́n ju ohun tí ènìyàn le è kà lọ.
Mnohé věci činíš ty, Hospodine Bože můj, a divní jsou skutkové tvoji i myšlení tvá o nás; není, kdo by je pořád vyčísti mohl před tebou. Já chtěl-li bych je vymluviti a vypraviti, mnohem více jich jest, nežli vypraveno býti může.
6 Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́, ìwọ ti ṣí mi ní etí. Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò béèrè.
Oběti a daru neoblíbils, ale uši jsi mi otevřel; zápalu a oběti za hřích nežádal jsi.
7 Nígbà náà ni mo wí pé, “Èmi nìyí; nínú ìwé kíká ni a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
Tehdy řekl jsem: Aj, jduť, jakož v knihách psáno jest o mně.
8 Mo ní inú dídùn láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ, ìwọ Ọlọ́run mi, òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
Abych činil vůli tvou, Bože můj, líbost mám; nebo zákon tvůj jest u prostřed vnitřností mých.
9 Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà láàrín àwùjọ ńlá; wò ó, èmi kò pa ètè mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀, ìwọ Olúwa.
Ohlašoval jsem spravedlnost v shromáždění velikém; aj, rtů svých že jsem nezdržoval, ty znáš, Hospodine.
10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi; èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ. Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
Spravedlnosti tvé neukryl jsem u prostřed srdce svého, pravdu tvou a spasení tvé vypravoval jsem, nezatajil jsem milosrdenství tvého a pravdy tvé v shromáždění velikém.
11 Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
Ty pak, Hospodine, nevzdaluj slitování svých ode mne; milosrdenství tvé a pravda tvá vždycky ať mne ostříhají.
12 Nítorí pé àìníye ibi ni ó yí mi káàkiri, ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi, títí tí èmi kò fi ríran mọ́; wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, àti wí pé àyà mí ti kùnà.
Neboť jsou mne obklíčily zlé věci, jimž počtu není; dostihly mne mé nepravosti, tak že prohlédnouti nemohu; rozmnožily se nad počet vlasů hlavy mé, a srdce mé opustilo mne.
13 Jẹ́ kí ó wù ọ́, ìwọ Olúwa, láti gbà mí là; Olúwa, yára láti ràn mí lọ́wọ́.
Račiž ty mne, Hospodine, vysvoboditi; Hospodine, pospěšiž ku pomoci mé.
14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì kí wọn kí ó sì dààmú; àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n, àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Zahanbeni buďte, a zapyřte se všickni, kteříž hledají duše mé, aby ji zahladili; zpět obráceni a v potupu dáni buďte, kteříž líbost mají v neštěstí mém.
15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!” ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
Přijdiž na ně spuštění za to, že mne k hanbě přivésti usilují, říkajíce: Hahá, hahá.
16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ kí ó máa yọ̀ kí inú wọn sì máa dùn sí ọ; kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ kí o máa wí nígbà gbogbo pé, “Gbígbéga ni Olúwa!”
Ale ať radují a veselí se v tobě všickni hledající tebe, a milující spasení tvé ať říkají vždycky: Veleslaven budiž Hospodin.
17 Bí ó ṣe ti èmi ni, tálákà àti aláìní ni èmi, ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi àti ìgbàlà mi; má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́, ìwọ Ọlọ́run mi.
Já pak ačkoli chudý a nuzný jsem, Pán však pečuje o mne. Pomoc má a vysvoboditel můj ty jsi. Bože můj, neprodlévejž.

< Psalms 40 >