< Psalms 40 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa; ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
Aka mawt ham David kah Tingtoenglung BOEIPA te ka lamtawn rhoela ka lamtawn dongah kai taengla ha hooi tih ka pang ol a yaak.
2 Ó fà mí yọ gòkè láti inú ihò ìparun, láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀, ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta, ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
Te dongah longlonah tangrhom, sihnok tangnong lamkah kai n'koeih tih ka kho te thaelpang dongla m'pai sak phoeiah ka khokan a cikngae sak.
3 Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu, àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa. Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Te phoeiah mamih Pathen koehnah ham laa thai te ka ka dongah han khueh tih a yet loh a hmuh uh vaengah a rhih uh vetih BOEIPA dongah pangtung uh ni.
4 Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga, tàbí àwọn tí ó yapa lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
BOEIPA te amah kah pangtungnah la aka khueh hlang te a yoethen tih hlang oek neh laithae vilvak taengla mael pawh.
5 Olúwa Ọlọ́run mi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe. Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa; ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ, tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn, wọ́n ju ohun tí ènìyàn le è kà lọ.
Aw BOEIPA ka Pathen namah loh namah kah khobaerhambae muep na saii dongah kaimih ham na kopoek te nang taengah aka tae pawh. Ka puen tih ka thui te ka doek lakah tahoeng coeng.
6 Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́, ìwọ ti ṣí mi ní etí. Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò béèrè.
Hmueih neh khosaa te na hmae moenih. Kai ham hna nan vueh tih hmueihhlutnah neh boirhaem khaw na hoe moenih.
7 Nígbà náà ni mo wí pé, “Èmi nìyí; nínú ìwé kíká ni a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
Te dongah, “Cabu cayol khuiah kai ham a daek bangla ka lo coeng tih
8 Mo ní inú dídùn láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ, ìwọ Ọlọ́run mi, òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”
Ka Boeipa Pathen na kolonah saii ham ka hmae tih na olkhueng loh ka ko khui ah om coeng he,” ka ti.
9 Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà láàrín àwùjọ ńlá; wò ó, èmi kò pa ètè mi mọ́, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀, ìwọ Olúwa.
Duengnah te hlangping a yet taengah ka phong tih ka kam ka khuem pawt he BOEIPA namah loh na ming.
10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi; èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ. Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.
Na duengnah te ka lungbuei khui ah ka thuh pawh. Na uepomnah neh loeihnah te ka thui coeng. Na sitlohnah neh uepomnah te hlangping a yet taengah ka phah pawh.
11 Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.
BOEIPA nang loh na haidamnah te, kai taengah na sihtaeh moenih. Na sitlohnah neh na oltak loh, kai n'kueinah yoeyah saeh.
12 Nítorí pé àìníye ibi ni ó yí mi káàkiri, ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi, títí tí èmi kò fi ríran mọ́; wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ, àti wí pé àyà mí ti kùnà.
Tae lek pawt hil ah yoethae loh kai taengah a li. Kamah kathaesainah loh kamah n'kae dogah sawt la huut pawh. Ka lu dongkah sam lakah yet tih ka lungbuei ka tlo-oeng sut.
13 Jẹ́ kí ó wù ọ́, ìwọ Olúwa, láti gbà mí là; Olúwa, yára láti ràn mí lọ́wọ́.
Aw BOEIPA, kai huul ham te m'moeithen mai dae. Aw BOEIPA, kai bomkung la ha tawn uh dae.
14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì kí wọn kí ó sì dààmú; àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n, àwọn tí ń wá ìpalára mi.
Ka hinglu khoengvoep ham aka mae rhoek te yak uh saeh lamtah a hmai tal uh boeih saeh. Kai kah yoethae aka omtoem rhoek khaw a hnuk la balkhong uh saeh lamtah a hmaithae uh saeh.
15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!” ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
Amih kah yahpohnah dongah kai te, “Ahuei ah uei,” aka ti rhoek te hal uh saeh.
16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ kí ó máa yọ̀ kí inú wọn sì máa dùn sí ọ; kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ kí o máa wí nígbà gbogbo pé, “Gbígbéga ni Olúwa!”
Nang aka tlap boeih namah dongah a ngaingaih la a kohoe uh saeh lamtah namah kah loeihnah aka ngaih rhoek tah, “BOEIPA te pomsang pai saeh,” ti uh yoeyah saeh.
17 Bí ó ṣe ti èmi ni, tálákà àti aláìní ni èmi, ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi àti ìgbàlà mi; má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́, ìwọ Ọlọ́run mi.
Ka mangdaeng tih ka khodaeng dae kai he Boeipa loh n'thoelh nawn saeh. Kai kah bomkung neh kai aka hlawt ka Pathen nang na uelh moenih.

< Psalms 40 >