< Psalms 4 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi. Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́, ìwọ Ọlọ́run òdodo mi. Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi; ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
برای سالار مغنیان برذوات اوتار. مزمور داود ای خدای عدالت من، چون بخوانم مرا مستجاب فرما. در تنگی مرا وسعت دادی. بر من کرم فرموده، دعای مرا بشنو.۱
2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú? Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?
‌ای فرزندان انسان تا به کی جلال من عار خواهد بود، و بطالت را دوست داشته، دروغ را خواهید طلبید؟ سلاه۲
3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀; Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.
اما بدانید که خداوند مرد صالح را برای خودانتخاب کرده است، و چون او را بخوانم خداوندخواهد شنید.۳
4 Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀, nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín, ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.
خشم گیرید و گناه مورزید. در دلها بربسترهای خود تفکر کنید و خاموش باشید. سلاه۴
5 Ẹ rú ẹbọ òdodo kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
قربانی های عدالت را بگذرانید و بر خداوندتوکل نمایید.۵
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?” Olúwa, jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,
بسیاری می‌گویند: «کیست که به ما احسان نماید؟» ای خداوند نور چهره خویش را بر مابرافراز.۶
7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.
شادمانی در دل من پدید آورده‌ای، بیشتر از وقتی که غله و شیره ایشان افزون گردید.۷
8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà, nítorí ìwọ nìkan, Olúwa, ni o mú mi gbé láìléwu.
بسلامتی می‌خسبم و به خواب هم می‌روم زیراکه تو فقط‌ای خداوند مرا در اطمینان ساکن می‌سازی.۸

< Psalms 4 >