< Psalms 4 >
1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi. Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́, ìwọ Ọlọ́run òdodo mi. Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi; ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
Jusqu'à la Fin, un cantique de David dans les Psaumes. Lorsque je l'eus invoqué, le Dieu de ma justice, il m'exauça; tu m'as dilaté en mon affliction. Aie pitié de moi, et exauce ma prière!
2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú? Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?
Fils des hommes, jusques à quand aurez-vous le cœur appesanti? D'où vient que tous aimez la vanité, et cherchez le mensonge? Interlude.
3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀; Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.
Sachez donc que le Seigneur a rendu son Saint admirable; le Seigneur m'exaucera, lorsque je crierai vers lui.
4 Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀, nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín, ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.
Indignez-vous, mais ne péchez pas; soyez touchés de componction de ce que vous méditez sur votre couche au fond de vos cœurs. Interlude.
5 Ẹ rú ẹbọ òdodo kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Offrez le sacrifice de justice, et espérez au Seigneur;
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?” Olúwa, jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,
Plusieurs disent: Qui nous fera voir les biens? Seigneur, la lumière de ta face est empreinte sur nous;
7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.
Tu as mis la joie dans mon cœur. [Mes ennemis] se sont multipliés dans l'abondance de leur pain, de leur vin, de leur huile.
8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà, nítorí ìwọ nìkan, Olúwa, ni o mú mi gbé láìléwu.
Pour moi, je m'endormirai et me reposerai dans la paix; parce que toi, Seigneur, par une grâce singulière, tu m'as établi dans l'espérance.