< Psalms 4 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi. Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́, ìwọ Ọlọ́run òdodo mi. Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi; ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
Přednímu zpěváku na neginot, žalm Davidův. Když volám, vyslyš mne, Bože spravedlnosti mé. Ty jsi mi v úzkosti prostranství způsoboval, smiluj se nade mnou, a vyslyš modlitbu mou.
2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú? Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?
Synové lidští, dokudž sláva má v potupě bude? Dlouho-liž marnost milovati a lži hledati budete? (Sélah)
3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀; Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.
Vězte, žeť jest oddělil Hospodin sobě milého. Vyslyšíť mne Hospodin, když k němu volati budu.
4 Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀, nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín, ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.
Uleknětež se a nehřešte, přemyšlujte o tom v srdci svém, na ložci svém, a umlkněte. (Sélah)
5 Ẹ rú ẹbọ òdodo kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Obětujte oběti spravedlnosti, a doufejte v Hospodina.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, “Ta ni yóò ṣe rere fún wa?” Olúwa, jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,
Mnozí říkají: Ó bychom viděti mohli dobré věci. Hospodine, pozdvihni nad námi jasného oblíčeje svého,
7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.
I způsobíš radost v srdci mém větší, než oni mívají, když obilé a víno jejich se obrodí.
8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà, nítorí ìwọ nìkan, Olúwa, ni o mú mi gbé láìléwu.
Jáť u pokoji i lehnu i spáti budu; nebo ty, Hospodine, sám způsobíš mi bydlení bezpečné.

< Psalms 4 >