< Psalms 39 >

1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Saamu Dafidi. Mo wí pé, “Èmi yóò ṣọ́ ọ̀nà mi kí èmi kí ó má fi ahọ́n mi ṣẹ̀; èmi yóò fi ìjánu kó ara mi ní ẹnu níwọ̀n ìgbà tí ènìyàn búburú bá ń bẹ ní iwájú mi.”
Зичям: „Вой вегя асупра кэилор меле, ка сэ ну пэкэтуеск ку лимба; ымь вой пуне фрыу гурий кыт ва ста чел рэу ынаинтя мя.”
2 Mo fi ìdákẹ́ ya odi; mo tilẹ̀ pa ẹnu mi mọ́ kúrò nínú ọ̀rọ̀ rere; ìbànújẹ́ mi sì pọ̀ sí i.
Ам стат мут, ын тэчере; ам тэкут, мэкар кэ ерам ненорочит, ши тотушь дуреря мя ну ера май пуцин маре.
3 Àyà mi gbóná ní inú mi. Nígbà tí mo ń ṣàṣàrò, iná ràn; nígbà náà ni mo fi ahọ́n mi sọ̀rọ̀:
Ымь ардя инима ын мине, ун фок лэунтрик мэ мистуя, ши атунч мь-а венит кувынтул пе лимбэ ши ам зис:
4 “Olúwa, jẹ́ kí èmi kí ó mọ òpin mi, àti ìwọ̀n ọjọ́ mi, bí ó ti rí kí èmi kí o le mọ ìgbà tí mó ní níhìn-ín.
„Доамне, спуне-мь каре есте сфыршитул веций меле, каре есте мэсура зилелор меле, ка сэ штиу кыт де трекэтор сунт!”
5 Ìwọ ti ṣe ayé mi bí ìbú àtẹ́lẹwọ́, ọjọ́ orí mi sì dàbí asán ní iwájú rẹ. Dájúdájú olúkúlùkù ènìyàn nínú ìjókòó rere rẹ̀ jásí asán pátápátá. (Sela)
Ятэ кэ зилеле меле сунт кыт ун лат де мынэ ши вяца мя есте ка о нимика ынаинтя Та. Да, орьче ом есте доар о суфларе, орькыт де бине с-ар цине.
6 “Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji. Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán; wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ, wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.
Да, омул умблэ ка о умбрэ, се фрэмынтэ деӂяба, стрынӂе ла коморь ши ну штие чине ле ва луа.
7 “Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, Olúwa, kín ni mo ń dúró dè? Ìrètí mí ń bẹ ní ọ̀dọ̀ rẹ.
Акум, Доамне, че май пот нэдэждуи еу? Ын Тине ымь есте нэдеждя.
8 Gbà mí lọ́wọ́ ìrékọjá mi gbogbo. Kí o má sì sọ mí di ẹni ẹ̀gàn àwọn ènìyàn búburú.
Избэвеште-мэ де тоате фэрэделеӂиле меле! Ну мэ фаче де окара челуй небун!
9 Mo dákẹ́ jẹ́ẹ́; èmi kò sì ya ẹnu mi, nítorí wí pé ìwọ ni ó ṣe é.
Стау мут, ну дескид гура, кэч Ту лукрезь.
10 Mú pàṣán rẹ kúrò ní ara mi; èmí ṣègbé tán nípa lílù ọwọ́ rẹ.
Абате-Ць ловитуриле де ла мине! Ымь есе суфлетул суб ловитуриле мыний Тале.
11 Ìwọ fi ìbáwí kìlọ̀ fún ènìyàn nítorí ẹ̀ṣẹ̀, ìwọ a mú ẹwà rẹ parun bí kòkòrò aṣọ; nítòótọ́ asán ni ènìyàn gbogbo.
Ту педепсешть пе ом ши-л ловешть пентру фэрэделеӂя луй; ый прэпэдешть, ка молия, че аре ел май скумп. Да, орьче ом есте доар о суфларе.
12 “Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, kí o sì fetí sí igbe mi; kí o má ṣe di etí rẹ sí ẹkún mi. Nítorí àlejò ni èmi lọ́dọ̀ rẹ, àti àtìpó, bí gbogbo àwọn baba mi ti rí.
Аскултэ-мь ругэчуня, Доамне, ши плякэ-Ць урекя ла стригэтеле меле! Ну тэчя ын фаца лакримилор меле! Кэч сунт ун стрэин ынаинтя Та, ун прибяг, ка тоць пэринций мей.
13 Dá mi sí, kí èmi lè ní agbára, kí èmi tó lọ kúrò níhìn-ín yìí, àti kí èmi ó tó ṣe aláìsí.”
Абате-Ць привиря де ла мине ши ласэ-мэ сэ рэсуфлу, пынэ ну мэ дук ши сэ ну май фиу!

< Psalms 39 >