< Psalms 39 >
1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Saamu Dafidi. Mo wí pé, “Èmi yóò ṣọ́ ọ̀nà mi kí èmi kí ó má fi ahọ́n mi ṣẹ̀; èmi yóò fi ìjánu kó ara mi ní ẹnu níwọ̀n ìgbà tí ènìyàn búburú bá ń bẹ ní iwájú mi.”
Przewodnikowi chóru, Jedutunowi. Psalm Dawida. Powiedziałem: Będę strzegł moich dróg, abym nie zgrzeszył językiem; nałożę na usta wędzidło, dopóki niegodziwy [będzie] przede mną.
2 Mo fi ìdákẹ́ ya odi; mo tilẹ̀ pa ẹnu mi mọ́ kúrò nínú ọ̀rọ̀ rere; ìbànújẹ́ mi sì pọ̀ sí i.
Zaniemówiłem oniemiały, zamilkłem [nawet] w dobrej [sprawie], lecz moja boleść się wzmagała.
3 Àyà mi gbóná ní inú mi. Nígbà tí mo ń ṣàṣàrò, iná ràn; nígbà náà ni mo fi ahọ́n mi sọ̀rọ̀:
Rozgorzało we mnie serce; gdy rozmyślałem, zapłonął ogień, a [wtedy] mój język tak przemówił:
4 “Olúwa, jẹ́ kí èmi kí ó mọ òpin mi, àti ìwọ̀n ọjọ́ mi, bí ó ti rí kí èmi kí o le mọ ìgbà tí mó ní níhìn-ín.
PANIE, daj mi poznać mój kres i miarę moich dni, abym wiedział, jak jestem słaby.
5 Ìwọ ti ṣe ayé mi bí ìbú àtẹ́lẹwọ́, ọjọ́ orí mi sì dàbí asán ní iwájú rẹ. Dájúdájú olúkúlùkù ènìyàn nínú ìjókòó rere rẹ̀ jásí asán pátápátá. (Sela)
Oto wymierzyłeś moje dni na szerokość dłoni, a mój wiek jest niczym przed tobą; zaprawdę każdy człowiek, nawet najlepszy, jest całkowitą marnością. (Sela)
6 “Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji. Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán; wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ, wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.
Doprawdy człowiek przemija jak cień; doprawdy na próżno się kłopocze; gromadzi, a nie wie, kto to zabierze.
7 “Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, Olúwa, kín ni mo ń dúró dè? Ìrètí mí ń bẹ ní ọ̀dọ̀ rẹ.
A teraz czego mam oczekiwać, Panie? W tobie jest moja nadzieja.
8 Gbà mí lọ́wọ́ ìrékọjá mi gbogbo. Kí o má sì sọ mí di ẹni ẹ̀gàn àwọn ènìyàn búburú.
Uwolnij mnie od wszystkich moich występków, nie wystawiaj mnie na pośmiewisko głupca.
9 Mo dákẹ́ jẹ́ẹ́; èmi kò sì ya ẹnu mi, nítorí wí pé ìwọ ni ó ṣe é.
Zamilkłem i nie otworzyłem moich ust, bo ty [to] sprawiłeś.
10 Mú pàṣán rẹ kúrò ní ara mi; èmí ṣègbé tán nípa lílù ọwọ́ rẹ.
Oddal ode mnie twoje karanie, bo ginę od uderzeń twojej ręki.
11 Ìwọ fi ìbáwí kìlọ̀ fún ènìyàn nítorí ẹ̀ṣẹ̀, ìwọ a mú ẹwà rẹ parun bí kòkòrò aṣọ; nítòótọ́ asán ni ènìyàn gbogbo.
Gdy karą chłoszczesz człowieka za nieprawość, [to] jak mól niszczysz jego piękno; doprawdy marnością jest każdy człowiek. (Sela)
12 “Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, kí o sì fetí sí igbe mi; kí o má ṣe di etí rẹ sí ẹkún mi. Nítorí àlejò ni èmi lọ́dọ̀ rẹ, àti àtìpó, bí gbogbo àwọn baba mi ti rí.
Wysłuchaj mojej modlitwy, PANIE, i nakłoń ucha na moje wołanie; nie bądź głuchy na moje łzy, bo jestem gościem u ciebie [i] przychodniem, jak wszyscy moi ojcowie.
13 Dá mi sí, kí èmi lè ní agbára, kí èmi tó lọ kúrò níhìn-ín yìí, àti kí èmi ó tó ṣe aláìsí.”
Oszczędzaj mnie, abym się wzmacniał, zanim odejdę i już mnie nie będzie.