< Psalms 39 >

1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Saamu Dafidi. Mo wí pé, “Èmi yóò ṣọ́ ọ̀nà mi kí èmi kí ó má fi ahọ́n mi ṣẹ̀; èmi yóò fi ìjánu kó ara mi ní ẹnu níwọ̀n ìgbà tí ènìyàn búburú bá ń bẹ ní iwájú mi.”
Kumqondisi wokuhlabela. ElikaJeduthuni. Ihubo likaDavida. Ngathi, “Ngizaziqaphela izindlela zami, ngiluthinte ulimi lwami esonweni; ngizawugcika umlomo wami nxa ababi bekhona phambi kwami.”
2 Mo fi ìdákẹ́ ya odi; mo tilẹ̀ pa ẹnu mi mọ́ kúrò nínú ọ̀rọ̀ rere; ìbànújẹ́ mi sì pọ̀ sí i.
Kodwa kwathi lapho ngithule ngithe zwi, ngingatsho lutho loba lungoluhle ubuhlungu benhliziyo yami bakhula.
3 Àyà mi gbóná ní inú mi. Nígbà tí mo ń ṣàṣàrò, iná ràn; nígbà náà ni mo fi ahọ́n mi sọ̀rọ̀:
Inhliziyo yami yavutha ngaphakathi kwami; kwathi lapho ngizuliswa yimicabango, umlilo wavutha; ngasengikhuluma ngolimi lwami:
4 “Olúwa, jẹ́ kí èmi kí ó mọ òpin mi, àti ìwọ̀n ọjọ́ mi, bí ó ti rí kí èmi kí o le mọ ìgbà tí mó ní níhìn-ín.
“Ngitshengisa, Thixo, isiphetho sempilo yami lobunengi bezinsuku zami; ngazisa ukuthi impilo yami igijima kanganani.
5 Ìwọ ti ṣe ayé mi bí ìbú àtẹ́lẹwọ́, ọjọ́ orí mi sì dàbí asán ní iwájú rẹ. Dájúdájú olúkúlùkù ènìyàn nínú ìjókòó rere rẹ̀ jásí asán pátápátá. (Sela)
Usuwenze insuku zami zaba lobubanzi besandla; ububanzi beminyaka yami kabusilutho kuwe. Impilo yabantu ingumoya kuphela, kanye lalabo abakhanya behlalisekile.
6 “Nítòótọ́ ni olúkúlùkù ń rìn kiri bí òjìji. Nítòótọ́ ni wọ́n ń yọ ara wọn lẹ́nu lórí asán; wọ́n ń kó ọrọ̀ jọ, wọn kò sì mọ ẹni tí yóò ko lọ.
Umuntu uhambahamba njengesithunzi nje; uyatshikatshika, kodwa konke akwenzayo kuyize lodwa; ubuthelela inotho engazi ukuthi izakuba ngekabani.
7 “Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, Olúwa, kín ni mo ń dúró dè? Ìrètí mí ń bẹ ní ọ̀dọ̀ rẹ.
Kodwa okwamanje, Thixo, ngisafunani kambe? Ithemba lami likuwe.
8 Gbà mí lọ́wọ́ ìrékọjá mi gbogbo. Kí o má sì sọ mí di ẹni ẹ̀gàn àwọn ènìyàn búburú.
Ngisindisa kuzozonke iziphambeko zami; ungangenzi inhlekisa yezitha.
9 Mo dákẹ́ jẹ́ẹ́; èmi kò sì ya ẹnu mi, nítorí wí pé ìwọ ni ó ṣe é.
Ngathula; ngangingeke ngiwuvule umlomo wami, ngoba lokhu kwenziwe nguwe.
10 Mú pàṣán rẹ kúrò ní ara mi; èmí ṣègbé tán nípa lílù ọwọ́ rẹ.
Susa uswazi lwakho kimi; sengikhulelwa yisidutshulo sesandla sakho.
11 Ìwọ fi ìbáwí kìlọ̀ fún ènìyàn nítorí ẹ̀ṣẹ̀, ìwọ a mú ẹwà rẹ parun bí kòkòrò aṣọ; nítòótọ́ asán ni ènìyàn gbogbo.
Abantu uyabakhuza ubajezisele isono sabo; ucikiza inotho yabo njengenondo ngempela umuntu ngamunye ungumoya nje.
12 “Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa, kí o sì fetí sí igbe mi; kí o má ṣe di etí rẹ sí ẹkún mi. Nítorí àlejò ni èmi lọ́dọ̀ rẹ, àti àtìpó, bí gbogbo àwọn baba mi ti rí.
Zwana umkhuleko wami, Oh Thixo, lalela isikhalazo sami ngicela uncedo; ungabi ligcikandlebe nxa ngikhala. Phela ngihlala lawe nginjengesihambi, ngiyisethekeli njengoba okhokho bonke babenjalo.
13 Dá mi sí, kí èmi lè ní agbára, kí èmi tó lọ kúrò níhìn-ín yìí, àti kí èmi ó tó ṣe aláìsí.”
Ake ukhangele eceleni nje ukuze ngithokoze njalo, ngingakasuki lapha ngibe ngongasekho.”

< Psalms 39 >