< Psalms 38 >

1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Um salmo de David, para um memorial. Yahweh, não me repreenda em sua ira, nem me castigam em seu desgosto quente.
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Pois suas setas me furou, sua mão pressiona com força sobre mim.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
There não é nenhuma solidez em minha carne por causa de sua indignação, nem há nenhuma saúde nos meus ossos por causa do meu pecado.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Pois minhas iniqüidades passaram por cima de mim. Como um fardo pesado, eles são pesados demais para mim.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Minhas feridas são repugnantes e corruptas por causa da minha tolice.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
I estou com dores e me curvo muito. Eu vou de luto o dia todo.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Pois minha cintura está cheia de queimaduras. Não há solidez em minha carne.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Estou desmaiado e gravemente ferido. Eu gemi por causa da angústia do meu coração.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Lord, todo meu desejo está diante de vocês. Meu gemido não é escondido de você.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Meu coração palpita. Minha força me falha. Quanto à luz dos meus olhos, ela também me deixou.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Meus amantes e meus amigos estão distantes da minha praga. Meus parentes estão muito longe.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
They também que buscam minha vida, colocam armadilhas. Aqueles que procuram minha dor falam coisas maliciosas, e meditar enganos durante todo o dia.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
Mas eu, como surdo, não ouço. Eu sou como um homem mudo que não abre a boca.
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
Yes, eu sou como um homem que não ouve, em cuja boca não há repreensões.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
Pois espero em você, Yahweh. Vós respondereis, Senhor meu Deus.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
Pois eu disse: “Não os deixe se vangloriarem de mim”, ou se exaltam sobre mim quando meu pé escorrega”.
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Pois eu estou pronto para cair. Minha dor está continuamente diante de mim.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Pois eu vou declarar minha iniquidade. Lamentarei por meu pecado.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
Mas meus inimigos são vigorosos e muitos. Aqueles que me odeiam sem razão são numerosos.
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
They que fazem o mal pelo bem também são adversários para mim, porque eu sigo o que é bom.
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Don não me abandona, Yahweh. Meu Deus, não esteja longe de mim.
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Hurry para me ajudar, Senhor, minha salvação.

< Psalms 38 >