< Psalms 38 >
1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Ra Anumzamoka krimpa ahenantenka kea onasuge, karimpa ahenantenka knazana naminka nazeri fatgo hugera osuo!
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Keve ka'anura nahankeno nagu'a unefregenka, kazanura rentrako hunka narehapanetine.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Krimpama ahenantana zamo higena kria enerugeno, kuminimo higeno zaferinanimo'a natanegrie.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Na'ankure kumini'mo'a ome ra huno nazeri agateregeno, kna'amo'a narerari nehie.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Nagri'a neginagi navu'navazamo higeno hi'mnage namumo'a navufgarega tusiza huno hantohanto nehie.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Hagi tusi nata negrige'na pripri hu'na vano nehu'na, maka kna natagura nehu'na zavi krafa nehue.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Hagi namagenamo'a teve ha' nehuno, natanegrige'na kri e'nerue.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Ana nehuno hankaveni'a omnege'na tusiza hu'na havizantfa hue. Nagu'afinti'ma natamagria zamo hige'na kragira neruna krafa nehue.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Ra Anumzamoka, nagri'ma navesi'a zana maka Kagra ko' kenka antahinka hu'nane. Kragi'ma nerua zana Kagra nentahine.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Tumo'nimo'a fakro fakro nehigeno, hankaveni'a nomanegeno, navuragamo'a asu nehie.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Hagi zamavesima nezmantoa vahe'mo'zane, aronenimo'zanena, kri ruvazirante zankure hu'za koro nehu'za afete nemanize. Nagri'a koramo'zanena anagege nehu'za afete nemanize.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
Hagi ha' vahe'nimo'za nahenaku krifua anagintere nehazageno, nagri'ma nazeri haviza hunaku'ma nehaza vahe'mo'za, maka zupa nagri'ma nazeri havizama hanaza keagage retro nehaze.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
Nagra agesa ankanire vahe'mo'ma nehiaza hu'na kea nontahi'na, kema nosia vahe'mo'ma agi'ma hamunkino maniaza hu'noe.
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
Nagra zamagesa ankanire vahe'mo'zama nehazaza hu'na kea nontahi'na kenona huozamante'noe.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
Ra Anumzamoka kavega ante'na mani'noanki, Kagra kenona hunanto. Kagra Ra Anumzana nagri Anumza mani'nane.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
Nagra amanage hu'na nunamuna hu'na kasmi'noe, zamatrege'za ha' vahe'nimo'za traka'ma hanua zankura nagizana nere'za musena osiho hu'na kasami'noe.
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Na'ankure nata zamo'a mevava huno nevige'na, traka hu'za nehue.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Hianagi nagra kefo avu'ava'zama hu'noa zana huama hu'na negasami'na, tusi nasunku nehue.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
Hagi hankavemati'za ha'ma renenantaza ha' vahe'nimo'za agafa'a omne zante zamago ate'nenantaze.
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
Knare avu'ava'ma huzmantorera kefo avu'ava zanu nona hunante'naze. Na'ankure nagra knare avu'ava nehuge'za ha'renantaze
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Ra Anumzana nagri Ra Anumzamoka onatrege, natrenka afetera vugera osuo.
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Ra Anumzana nagu'vazi Anumzamoka ame hunka eme nazahuo.