< Psalms 38 >

1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Zsoltár Dávidtól. Emlékeztetésül. Őrökkévaló, ne a te haragodban büntess engem, és ne hevedben fenyíts engem!
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Mert nyílaid belém sülyedtek és reám sülyedt a kezed.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Nincs épség húsomban haragvásod miatt, nincs egészség csontjaimban vétkem miatt.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Mert bűneim túlhaladtak fejemen, nehéz teherhént nagyon is nehezek nekem.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Megbűzhödtek, senyvedtek sebeim oktalanságom miatt.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Lehorgadtam. meggörnyedtem felette nagyon, egész nap elbúsultan jártam.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Mert ágyékaim telve vannak üszöggel és nincsen épség húsomban.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Megdermedtem és megtörődtem felette nagyon, ordítottam szívem sohajtásától.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Uram, előtted minden hivánságom, és nyögésem nincs elrejtve előled.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Szívem hánytorog, elhagyott erőm, szemeim világossága – az sincs meg nálam.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Barátaim és társaim csapásommal szemben félre állanak, és a hozzám közel levők messzünnen álltak meg.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
Tőrt vetettek, kik életemre törnek, és a kik bajomat keresik, veszedelmeket beszélnek, és csalásokat szólnak egész nap.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
De én akár a süket nem hallok és akár a néma, a ki nem nyitja föl száját.
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
Olyan lettem mint férfi, a ki nem hall, s a kinek szájában nincsenek ellenvetések.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
Mert reád, Örökkévaló, várakoztam, te felelsz majd Uram, Istenem.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
Mert azt mondtam: csak ne örüljenek rajtam, midőn lábam megtántorodott, fenhéjáztak ellenem.
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Mert én bukásra vagyok elkészülve, és fájdalmam mindég előttem van.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Mert jelentem bűnömet, aggódom vétkem miatt.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
De ellenségeim életben vannak, hatalmasak, és sokan vannak, kik engem hazugul gyűlölnek:
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
s a kik rosszal fizetnek jóért, megvádolnak azért, hogy jóra törekedtem.
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Ne hagyj el, Örökkévaló; Istenem, ne légy távol tőlem.
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Siess segítségemre, Uram, segedelmem!

< Psalms 38 >