< Psalms 38 >

1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Thaburi ya Daudi Wee Jehova, ndũkandũithie ũrĩ na marakara, kana ũũherithie ũrĩ na mangʼũrĩ.
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Nĩgũkorwo mĩguĩ yaku nĩĩtheceete, na guoko gwaku nĩ kũũhũrĩte mũno.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Ndirĩ na ũgima wa mwĩrĩ tondũ wa mangʼũrĩ maku; mahĩndĩ makwa nĩmarũaru nĩ ũndũ wa mehia makwa.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Mahĩtia makwa nĩmanditũhĩire mũno o ta mũrigo mũritũ itangĩhota gũkuua.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Ironda ciakwa nĩitogotete na ikanunga nĩ tondũ wa ũrimũ wakwa wa mehia.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Thiiaga ndĩĩhacĩte, ngakungĩrĩra mũno, mũthenya wothe ndindaga ngĩcakaya.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Mũgongo wakwa ũiyũrĩtwo nĩ ruo ta rwa mwaki; ndirĩ na ũgima wa mwĩrĩ.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Ndĩ mũmocu na ngathuthĩka biũ; ndĩracaaya nĩ ruo rwa ngoro.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Wee Mwathani, wendi wakwa wothe ũrĩ o mbere yaku; gũcaaya gwakwa ti kũhitharu harĩwe.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Ngoro yakwa nĩĩratuuma mũno, naguo hinya wakwa nĩgũthira ũrathira; o na ũtheri nĩumĩte maitho-inĩ makwa.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Arata na athiritũ akwa matiendaga kũnguhĩrĩria nĩ ũndũ wa ironda ciakwa; o na andũ a itũũra rĩakwa manjikaraga haraihu.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
Andũ arĩa mendaga kũnjũraga nĩ mĩtego mandegagĩra, arĩa mendaga kũnjĩka ũũru maaragia ũrĩa mangĩnyũnũha; mũthenya wothe mathugundaga o maheeni.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
Niĩ haana ta mũndũ gĩtaigua, ũrĩa ũtaiguaga, ngahaana ta mũndũ ũtaaragia, ũrĩa ũtangĩtumũra kanua gake;
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
nduĩkĩte ta mũndũ ũtaiguaga, ũrĩa kanua gake gatarĩ ũndũ kangĩhota gũcookia.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
Wee Jehova, Wee nĩwe njetagĩrĩra; Wee Mwathani Ngai wakwa, Wee nĩwe ũkũnjookeria ũhoro.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
Nĩgũkorwo ndoigire atĩrĩ, “Ndũkanareke thũ ciakwa ingenerere, o na kana ciĩtũũgĩrie igũrũ rĩakwa rĩrĩa kũgũrũ gwakwa gwatenderũka.”
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Nĩgũkorwo ngirie kũgũa, na njikaraga ndĩ na ruo hĩndĩ ciothe.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Nĩngumbũra waganu wakwa; nĩthĩĩnĩtio nĩ mehia makwa.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
Thũ ciakwa iria irĩ kĩyo nĩcio nyingĩ; arĩa maathũire hatarĩ gĩtũmi nĩ aingĩ.
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
Andũ arĩa mandĩhaga wega wakwa na ũũru manjambagia rĩrĩa niĩ ngũthingata ũndũ ũrĩa mwega.
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Wee Jehova, ndũkandiganĩrie; Wee Ngai wakwa, ndũgaikare haraihu na niĩ.
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Ũka narua ũndeithie, Wee Mwathani, Mũhonokia wakwa.

< Psalms 38 >