< Psalms 38 >

1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Psaume de David. — Pour servir de mémorial. Éternel, ne me châtie pas, dans ta colère. Et ne me punis pas, dans ton courroux!
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Car tes flèches m'ont atteint, Et ta main s'est appesantie sur moi.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Ton courroux n'a épargné aucune partie de mon corps; Mon péché ne laisse aucun répit à mon corps.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Car mes iniquités s'élèvent au-dessus de ma tête; Elles sont comme un lourd fardeau, trop pesant pour moi.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Mes plaies sont fétides et purulentes, A cause de mes égarements.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Je suis courbé, abattu jusqu'au dernier point; Je marche en habit de deuil tout le jour.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Un feu ardent consume mes reins; Aucune partie de mon corps n'a été épargnée.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Je suis accablé et tout brisé; Je rugis dans le frémissement de mon coeur.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Seigneur, tous mes désirs sont devant toi, Et mes soupirs ne te sont point cachés.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Mon coeur palpite, ma force m'abandonne, Et la lumière même de mes yeux me fait défaut.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Mes amis, mes compagnons s'éloignent de ma plaie, Et mes proches se tiennent à distance.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
Ceux qui en veulent à ma vie me tendent des pièges; Ceux qui cherchent ma perte tiennent des propos meurtriers; Ils ne songent qu'à dresser contre moi leurs embûches.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
Mais moi, comme un sourd, je n'entends pas; Comme un muet, je n'ouvre pas la bouche.
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
Je suis comme un homme qui n'entend pas. Et qui n'a point de réplique sur les lèvres.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
C'est en toi, ô Éternel, que je mets mon espérance: Tu m'exauceras, ô Seigneur, mon Dieu!
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
J'ai dit: Ne permets pas qu'ils triomphent à mon sujet. Ceux qui me traitent avec mépris, quand mon pied chancelle!
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Car je suis près de tomber. Et ma douleur est toujours devant moi.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Je confesse mon iniquité; Je suis dans la crainte, à cause de mon péché.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
Cependant, mes ennemis sont pleins de vie et de force; Ceux qui me haïssent sans motif sont nombreux,
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
Et, me rendant le mal pour le bien. Ils se font mes adversaires, parce que je m'attache au bien.
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Ne m'abandonne pas, ô Éternel! Mon Dieu, ne t'éloigne pas de moi!
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Hâte-toi, viens à mon secours. Seigneur, toi qui es ma délivrance!

< Psalms 38 >