< Psalms 38 >
1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Psaume de David. Pour faire souvenir. Yahweh, ne me punis pas dans ta colère, et ne me châtie pas dans ta fureur.
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Car tes flèches m’ont atteint, et ta main s’est appesantie sur moi.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Il n’y a rien de sain dans ma chair à cause de ta colère, il n’y a rien de sauf dans mes os à cause de mon péché.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Car mes iniquités s’élèvent au-dessus de ma tête; comme un lourd fardeau, elles m’accablent de leur poids.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Mes meurtrissures sont infectes et purulentes, par l’effet de ma folie.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Je suis courbé, abattu à l’excès; tout le jour je marche dans le deuil.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Un mal brûlant dévore mes reins, et il n’y a rien de sain dans ma chair.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Je suis sans force, brisé outre mesure; le trouble de mon cœur m’arrache des gémissements.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Seigneur, tous mes désirs sont devant toi, et mes soupirs ne te sont pas cachés.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Mon cœur palpite, ma force m’abandonne, et la lumière même de mes yeux n’est plus avec moi.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Mes amis et mes compagnons s’éloignent de ma plaie; et mes proches se tiennent à l’écart.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
Ceux qui en veulent à ma vie tendent leurs pièges; ceux qui cherchent mon malheur profèrent des menaces, et tout le jour ils méditent des embûches.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
Et moi, je suis comme un sourd, je n’entends pas; je suis comme un muet, qui n’ouvre pas la bouche.
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
Je suis comme un homme qui n’entend pas, et dans la bouche duquel il n’y a point de réplique.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
C’est en toi, Yahweh, que j’espère; toi, tu répondras, Seigneur, mon Dieu!
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
Car je dis: « Qu’ils ne se réjouissent pas à mon sujet, qu’ils ne s’élèvent pas contre moi, si mon pied chancelle. »
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Car je suis près de tomber, Et ma douleur est toujours devant moi.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Car je confesse mon iniquité, Je suis dans la crainte à cause de mon péché.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
Et mes ennemis sont pleins de vie, ils sont puissants; Ceux qui me haïssent sans cause se sont multipliés.
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
Ils me rendent le mal pour le bien; ils me sont hostiles, parce que je cherche la justice.
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Ne m’abandonne pas, Yahweh! Mon Dieu, ne t’éloigne pas de moi!
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Hâte-toi de me secourir, Seigneur, toi qui es mon salut!