< Psalms 38 >

1 Saamu Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe fi ìyà jẹ mí nínú ìrunú rẹ̀.
Žalm Davidův k připomínání. Hospodine, v prchlivosti své netresci mne, ani v hněvě svém kárej mne.
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin, ọwọ́ rẹ sì kì mí mọ́lẹ̀.
Nebo střely tvé uvázly ve mně, a ruka tvá na mne těžce dolehla.
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ; kò sí àlàáfíà nínú egungun mi nítorí i ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Nic není celého v těle mém pro tvou hněvivost, nemají pokoje kosti mé pro hřích můj.
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀; wọ́n tó ìwọ̀n bi àjàgà tí ó wúwo jù fún mi.
Nebo nepravosti mé vzešly nad hlavu mou, jako břímě těžké nemožné jsou mi k unesení.
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́ nítorí òmùgọ̀ mi.
Zahnojily se, a kyší rány mé pro bláznovství mé.
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi èmi ń ṣọ̀fọ̀ rìn kiri ní gbogbo ọjọ́.
Pohrbený a sklíčený jsem náramně, každého dne v smutku chodím.
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni kò sì ṣí ibi yíyè ní ara mi.
Nebo ledví má plná jsou mrzkosti, a nic není celého v těle mém.
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ; mo kérora nítorí ìrúkèrúdò àyà mi.
Zemdlen jsem a potřín převelice, řvu pro úzkost srdce svého.
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ; ìmí ẹ̀dùn mi kò sá pamọ́ fún ọ.
Pane, před tebou jest všecka žádost má, a vzdychání mé není před tebou skryto.
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀; bí ó ṣe ti ìmọ́lẹ̀ ojú mi ni, ó ti lọ kúrò lára mi.
Srdce mé zmítá se, opustila mne síla má, i to světlo očí mých není se mnou.
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi, àwọn alábágbé mi, dúró lókèèrè.
Ti, kteříž mne milovali, a tovaryši moji, štítí se ran mých, a příbuzní moji zdaleka stojí.
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi; àti àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára ń sọ̀rọ̀ nípa ìparun, wọ́n sì ń gbèrò ẹ̀tàn ní gbogbo ọjọ́.
Ti pak, kteříž stojí o bezživotí mé, osídla lécejí, a kteříž mého zlého hledají, mluví převráceně, a přes celý den lest a chytrost smýšlejí.
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀; àti bí odi, tí kò le sọ̀rọ̀.
Ale já jako hluchý neslyším, a jako němý, kterýž neotvírá úst svých;
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀, àti bí ẹnu ẹni tí kò sí ìjiyàn.
Tak jsem, jako člověk, kterýž neslyší, a v jehož ústech není žádného odporu.
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè; ìwọ ni, Olúwa Ọlọ́run mi, ẹni tí yóò dáhùn.
Nebo na tě, Hospodine, očekávám, ty za mne odpovíš, Pane Bože můj.
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí; nígbà tí ẹsẹ̀ mi bá yọ̀ wọn yóò máa gbé ara wọn ga sí mi.”
Nebo jsem řekl: Ať se neradují ze mne, poklesla-li by se noha má, ať se pyšně nepozdvihují nade mnou,
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú, ìrora mi sì wà pẹ̀lú mi nígbà gbogbo.
Poněvadž k snášení bíd hotov jsem, anobrž bolest má vždycky jest přede mnou.
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi; àánú sì ṣe mí fún ẹ̀ṣẹ̀ mi.
A že nepravosti své vyznávám, a pro hřích svůj tesklím.
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó kórìíra mi lọ́nà òdì.
Pročež nepřátelé moji veseli jsouce, silí se, a rozmnožují se ti, kteříž mne bez příčiny nenávidí.
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi àwọn ni ọ̀tá mi nítorí pé mò ń tọ ìre lẹ́yìn.
A zlým za dobré mi se odplacujíce, činí mi protivenství, proto že dobrého následuji.
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa! Ọlọ́run mi, má ṣe jìnnà sí mi.
Neopouštějž mne, Hospodine Bože můj, nevzdalujž se ode mne.
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́, Olúwa, Olùgbàlà mi.
Přispěj k spomožení mému, Pane spasení mého.

< Psalms 38 >