< Psalms 37 >

1 Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
Немој се жестити гледајући неваљале, немој завидети онима који чине безакоње.
2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
Јер се као трава брзо косе, и као зелено биље вену.
3 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Уздај се у Господа и твори добро; живи на земљи и храни истину.
4 Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
Теши се Господом, и учиниће ти шта ти срце жели.
5 Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Предај Господу пут свој, и уздај се у Њега, Он ће учинити.
6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
И извешће као видело правду твоју, и правицу твоју као подне.
7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
Ослони се на Господа, и чекај Га. Немој се жестити гледајући кога где напредује на путу свом, човека, који ради шта намисли.
8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Утишај гнев, и остави јарост; немој се дражити да зло чиниш.
9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
Јер ће се истребити који чине зло, а који чекају Господа наследиће земљу.
10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
Још мало, па неће бити безбожника; погледаћеш на место његово, а њега нема.
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
А смерни ће наследити земљу, и наслађиваће се множином мира.
12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
Зло мисли безбожник праведнику, и шкргуће на њ зубима својим.
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
Али му се Господ смеје, јер види да се примиче дан његов.
14 Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
Мач потежу безбожници, запињу лук свој, да оборе убогога и ништега и покољу оне који иду правим путем.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
Мач ће њихов ударити у њихово срце, и лукови њихови поломиће се.
16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
Боље је мало у праведника него богатство многих безбожника.
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
Јер ће се мишице безбожницима потрти, а праведнике утврђује Господ.
18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
Зна Господ дане безазленима, и део њихов траје довека.
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
Неће се постидети у зло доба, у дане гладне биће сити.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
А безбожници гину, и непријатељи Господњи као лепота шумска пролазе, као дим пролазе.
21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
Безбожник узаима и не враћа, а праведник поклања и даје.
22 nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
Јер које Он благослови, они наследе земљу, а које Он прокуне, они се истребе.
23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
Господ утврђује кораке сваког човека и мио Му је пут његов.
24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
Кад посрне да падне, неће пасти, јер га Господ држи за руку.
25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
Бејах млад и остарех, и не видех праведника остављеног, ни деце његове да просе хлеба.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
Сваки дан поклања и даје у зајам, и на наслеђу је његовом благослов.
27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
Уклањај се ода зла, и чини добро, и живи довека.
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
Јер Господ љуби праведни суд, и не оставља свеце своје; увек се они чувају; а племе ће се безбожничко истребити.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
Праведници ће наследити земљу, и живеће на њој довека.
30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
Уста праведникова говоре мудрост, и језик његов казује истину.
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
Закон је Бога његовог њему у срцу, стопала се његова не спотичу.
32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
Безбожник вреба праведника, и тражи да га убије;
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
Али га Господ неће пустити у руке његове, нити ће дати да га окриве кад се стану судити.
34 Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
Чекај Господа и држи се пута Његовог, и Он ће те поставити да владаш земљом; видећеш како ће се истребити безбожници.
35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
Видех безбожника страшног који се рашириваше као гранато дрво;
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
Али прође, и ево нема га; тражим га и не находим.
37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
Храни чистоту и пази правду, јер ће у човека мирног остати наслеђе.
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
А безаконика ће нестати сасвим; наслеђе ће се безбожничко затрти.
39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
Од Господа је спасење праведницима; Он је крепост њихова у невољи.
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
Господ ће им помоћи, и избавиће их; избавиће их од безбожника, и сачуваће их, јер се у Њега уздају.

< Psalms 37 >