< Psalms 37 >
1 Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
Öfundaðu aldrei vonda menn,
2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
því að fyrr en varir eru þeir fallnir og visna eins og grasið.
3 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Treystu heldur Drottni, vertu góðgjarn og sýndu kærleika. Þá muntu búa öruggur í landinu og farnast vel.
4 Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
Þú skalt gleðjast í Drottni – og hann mun veita þér það sem hjarta þitt þráir.
5 Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Fel Drottni framtíð þína, áform þín og verk, og treystu honum. Hann mun vel fyrir öllu sjá.
6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
Heiðarleiki þinn og hreinskilni verða öllum augljós, og Drottinn mun láta þig ná rétti þínum.
7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
Hvíldu í Drottni og treystu honum. Bíð þess í þolinmæði að hann hefjist handa. Öfunda ekki vonda menn sem vegnar vel.
8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Láttu af reiðinni! Slepptu heiftinni. Vertu ekki svekktur og áhyggjufullur – slíkt leiðir ekki til góðs.
9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
Þeir sem illt fremja verða þurrkaðir út, en þeir sem treysta Drottni eignast landið og gæði þess.
10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
Innan skamms verða guðleysingjarnir á bak og burt. Þegar þú leitar þeirra eru þeir horfnir.
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
En hinir hógværu fá landið til eignar, þeir munu hljóta blessun og frið.
12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
Drottinn hlær að þeim sem brugga launráð gegn hans trúuðu.
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
Hann hefur þegar ákveðið daginn er þeir verða dæmdir.
14 Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
Óguðlegir hyggja á illt gegn réttlátum, undirbúa blóðbað.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
En þeir munu farast fyrir eigin sverði og bogar þeirra verða brotnir.
16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
Betra er að eiga lítið og vera guðrækinn, en óguðlegur og hafa allsnægtir,
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
því að óguðlegir munu falla, en Drottinn annast sína trúuðu.
18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
Daglega skoðar Drottinn réttlætisverk trúaðra og reiknar þeim eilíf laun.
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
Hann styður þá í kreppunni og heldur lífinu í þeim í hallæri.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
Vantrúaðir farast og óvinir Guðs visna eins og grasið. Eins og sinu verður þeim brennt, þeir líða burt eins og reykur.
21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
Guðlaus maður tekur lán og borgar ekki, en hinn guðrækni er ónískur og gefur með gleði.
22 nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
Þeir sem Drottinn blessar eignast landið, en bannfærðum verður útrýmt.
23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
Drottinn stýrir skrefum hins guðrækna og gleðst yfir breytni hans.
24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
Þótt hann falli þá liggur hann ekki flatur því að Drottinn reisir hann á fætur.
25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
Ungur var ég og nú er ég gamall orðinn, en aldrei sá ég Drottin snúa baki við guðhræddum manni né heldur börn hans biðja sér matar.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
Nei, guðræknir menn eru mildir og lána og börn þeirra verða öðrum til blessunar.
27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
Viljir þú búa við frið og lifa lengi, þá forðastu illt en gerðu gott,
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
því að Drottinn hefur mætur á góðum verkum og yfirgefur ekki sína trúuðu, hann mun varðveita þá, en uppræta niðja óguðlegra.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
Hinir réttlátu fá landið til eignar og búa þar mann fram af manni.
30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
Guðrækinn maður talar speki, enda réttsýnn og sanngjarn.
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
Lögmál Guðs er í hjarta hans og hann kann að greina gott frá illu.
32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
Ranglátir menn njósna um réttláta, vilja þá feiga.
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
En Drottinn stöðvar áform illvirkjanna og sýknar réttláta fyrir dómi.
34 Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
Óttastu ekki, því að Drottinn mun svara bæn þinni! Gakktu hiklaust á hans vegum. Á réttum tíma mun hann veita þér velgengni og uppreisn æru. Þá muntu sjá illvirkjunum útrýmt.
35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
Ég sá vondan mann og hrokafullan – hann þandi sig út eins og laufmikið tré –
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
en svo var hann horfinn! Ég leitaði eftir honum, en fann hann ekki framar.
37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
En hvað um hinn ráðvanda og hreinskilna? Það er önnur saga! Því að góðir menn og friðsamir eiga framtíð fyrir höndum.
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
Illum mönnum verður útrýmt og þeir eiga enga framtíðarvon.
39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
Drottinn bjargar hinum guðræknu. Hann er þeim hjálp og skjól á neyðartímum.
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
Þeir treysta honum og því hjálpar hann þeim og frelsar þá frá vélráðum óguðlegra.