< Psalms 37 >

1 Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
Dávidtól. Ne gerjedj föl a gonosztevők ellen, ne irígykedj azokra, kik jogtalant mívelnek.
2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
Mert mint a fű gyorsan levágatnak, s mint zöld pázsit elhervadnak.
3 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Bízzál az Örökkévalóban és tégy jót, lakjál az országban és járj hűség után.
4 Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
S gyönyörködjél az Örökkévalóban, s megadja neked szíved kérelmeit.
5 Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Hárítsd az Örökkévalóra útadat, bízzál benne, ő majd megcselekszi;
6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
majd kihozza mint a világosságot igazadat, és jogodat, mint a déli fényt.
7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
Csendben várj az Örökkévalóra és várakozzál reá, ne gerjedj fel az ellen, ki szerencsés az útján, oly férfi ellen, ki fondorlatokat mível.
8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Hagyj föl a haraggal, hadd abban a fölhevülést, ne gerjedj fel csakis gonosztevésre visz.
9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
Mert a gonosztevők kiirtatnak, de kik az Örökkévalót remélik – ők fogják bírni az országot.
10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
Még egy kevés – s nincs gonosz, oda figyelj helyére a nincsen;
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
de az alázatosak bírni fogják az országot és gyönyörködni fognak a béke bőségében.
12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
Fondorkodik a gonosz az igaz ellen és vicsorítja rá fogát.
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
Az Úr nevet rajta, mert látta, hogy eljön a napja.
14 Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
Kardot rántottak a gonoszok és feszítotték íjjukat, hogy elejtseneh szegényt és szűkölködőt, hogy levágják az egyenes iítuakat.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
Kardjuk önnönszívükbe hat be, és íjjai eltöretnek.
16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
Jobb a kevés, a mi az igazé, mint sok gonosznak gazdagsága;
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
mert a gonoszok karjai eltöretnek, de az igazak támogatója az Örökkévaló.
18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
Ismeri az Örökkévaló a gáncstalanok napjait és birtokuk örökre meglesz.
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
Nem szégyenülnek meg bajnak idejében és éhinség napjaiban jóllaknak.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
Mert a gonoszok elvesznek, s az Örökkévaló ellenségei olyanok, mint a rétek dísze: elenyésztek, a füstben enyésztek el.
21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
Kölcsön vesz a gonosz és nem fizet, de az igaz könyörül és adakozik.
22 nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
Mert az ő áldottjai fogják bírni az országot, és az átkozottjai kiirtatnak.
23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
Az Örökkévalótól szilárdíttattak meg a férfi léptei, és útját kedveli;
24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
midőn elesik, nem hajíttatik el, mert az Örökkévaló támogatja kezét.
25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
Fiatal voltam, meg is öregedtem, de nem láttam igazat elhagyatva és magzatját, a mint kenyeret koldul.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
Egész nap könyörül és kölcsön ad, magzatja pedig áldásúl van.
27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
Távozz a rossztól, tégy jót, hogy örökre megmaradj.
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
Mert az Örökkévaló szereti a jogot, s nem hagyja el jámborait; örökké megőriztetnek, míg a gonoszok magzatja kiirtatik.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
Az igazak fogják bírni az országot és laknak mindétig rajta.
30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
Igaznak szája bölcsességet szól, és nyelve jogosságot beszél;
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
Istenének tana szívében van, nem inognak meg lépései.
32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
Leselkedik a gonosz az igazra, és arra tör, hogy megölje.
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
Az Örökkévaló nem hagyja meg kezében, s nem kárhoztatja el, midőn megitéltetik.
34 Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
Remélj az Örökkévalóhoz, és őrizd meg útját; majd felmagasít, hogy bírjad az országot, a gonoszok kiírtását nézed.
35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
Láttam egy gonoszt, erőszakost, s a ki terpeszkedett mint zöldelő honor fa:
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
elhaladtak arra, s íme nincsen; kerestem őt, de nem volt található.
37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
Vigyázd meg a gáncstalant és nézd az egyeneset, mert van jövője a béke emberének.
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
De az elpártolók megsemmisíttettek egyaránt, a gonoszok jövője kiírtatott.
39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
Az igazak segedelme pedig az Örökkévalótól van, erősségük ő a szorongatás idején.
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
Megsegítotte őket az Örökkévaló és megszabadította; megszabadítja a gonoszoktól és megvédi őket, mert benne kerestek menedéket.

< Psalms 37 >