< Psalms 37 >

1 Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
De David. Ne t'irrite pas au sujet des méchants; Ne porte pas envie à ceux qui font le mal.
2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
Car ils seront fauchés soudain comme l'herbe; Ils se faneront comme l'herbe verte.
3 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Confie-toi en l'Éternel, et fais le bien; Habite en paix le pays, et mets ton plaisir dans la fidélité.
4 Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
Fais de l'Éternel tes délices. Et il t'accordera ce que ton coeur demande.
5 Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Remets ton sort à l'Éternel; Confie-toi en lui, et il agira.
6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
Il fera éclater ta justice comme la lumière. Et ton droit comme le soleil en plein midi.
7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
Abandonne-toi en paix à l'Éternel, et mets ton espoir en lui. Ne t'irrite point. Quand tu vois un homme réussir dans ses entreprises, Et venir à bout de ses mauvais desseins.
8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Réprime la colère, et renonce au dépit; Ne t'irrite point: cela t'entraînerait au mal!
9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
En effet, les méchants seront exterminés; Mais ceux qui mettent leur confiance en l'Éternel, Ceux-là posséderont la terre!
10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
Encore un peu de temps, et le méchant ne sera plus; Tu regarderas la place où il était, et il aura disparu.
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
Mais les humbles posséderont la terre, Et ils jouiront d'une grande prospérité.
12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
Le méchant suscite des complots contre le juste, Et il grince des dents contre lui.
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
Le Seigneur se rit du méchant; Car il voit que le jour de son châtiment approche.
14 Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
Les méchants ont tiré l'épée et bandé leur arc. Pour abattre l'affligé et le pauvre, Pour égorger ceux qui suivent la voie droite.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
Leur épée entrera dans leur propre coeur, Et leurs arcs seront brisés.
16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
Le peu qui appartient au juste Vaut mieux que l'abondance de beaucoup de méchants.
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
Car la puissance des méchants sera brisée; Mais l'Éternel soutient les justes.
18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
L'Éternel veille sur les jours des hommes intègres, Et leur héritage subsiste à perpétuité.
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
Ils ne seront pas confus au temps du malheur; Ils seront rassasiés au jour de la famine.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
Car les méchants périront; Les ennemis de l'Éternel passeront comme la parure des prés; Ils périront, ils disparaîtront comme une fumée.
21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
Le méchant emprunte, et il ne rend pas; Mais le juste a compassion, et il donne.
22 nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
Ceux que Dieu bénit possèderont la terre; Mais ceux qu'il maudit seront exterminés.
23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
Les pas de l'homme de bien sont affermis par l'Éternel, Qui prend plaisir à lui montrer sa voie.
24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
S'il trébuche, il ne sera pas renversé; Car l'Éternel le soutient par la main.
25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
J'ai été jeune, et je suis devenu vieux; Mais je n'ai pas vu le juste abandonné, Ni ses enfants mendiant leur pain.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
Tous les jours il a compassion et il prête. Et sa postérité est bénie.
27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
Détourne-toi du mal et fais le bien. Et tu seras pour toujours en sécurité.
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
Car l'Éternel aime la justice: Il n'abandonne pas ses fidèles, qui sont gardés pour toujours; Mais la race des méchants sera exterminée.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
Les justes posséderont la terre. Et ils y demeureront à perpétuité.
30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
La bouche du juste annonce la sagesse. Et sa langue proclame la justice.
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
La loi de son Dieu est dans son coeur; Ses pas ne chancelleront point.
32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
Le méchant épie le juste, Et il cherche à le faire périr.
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
L'Éternel ne le laissera pas en son pouvoir; Il ne le condamnera pas à l'heure du jugement.
34 Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
Mets ta confiance en l'Éternel, et marche dans ses voies: Il t'élèvera et te fera posséder la terre. Et tu verras les méchants exterminés.
35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
J'ai vu le méchant au comble de la puissance, Et s'étendant comme un arbre vigoureux.
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
Il n'a fait que passer et voici qu'il n'est plus! Je l'ai cherché: je n'ai pu le trouver.
37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
Observe l'homme intègre, et regarde l'homme droit; Car il y a un avenir pour l'homme de paix!
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
Mais les pécheurs seront entièrement détruits: L'espoir des méchants sera anéanti.
39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
La délivrance des justes vient de l'Éternel: Il est leur rempart au temps de la détresse.
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
L'Éternel les secourt et les délivre; Il les délivre des méchants et les sauve. Parce qu'ils cherchent auprès de lui leur refuge.

< Psalms 37 >